Ifa religion: Àwọn Oníṣẹ̀ṣe ń fẹ́ kí Buhari fún wọn láàyè láti yanjú ìṣoro Naijiria lásìkò yìí

Oríṣun àwòrán, Ifashola Adedeji Durokifa
Ẹgbẹ awọn oniṣẹṣe nipinlẹ ogun ti ke si Aarẹ Muhammadu Buhari lati fun awọn laye lati yanju iṣoro to n koju ẹka eto abo Naijiria.
Oluwo Ifa ti ilu Egba, Oloye Ifagbeminiyi Baoku lo sọ ọrọ naa lasiko ayajọ ọjọ Iṣẹṣe ti ọdun 2021 to waye niluu Abeokuta.
Ayajọ ọjọ Iṣẹṣe naa jẹ ọjọ kan ti wọn maa n ya sọtọ nilẹ Yoruba fun awọn ẹlẹsin ibilẹ lati sin awọn oriṣa wọn.
- Tinubu lẹ́tọ̀ọ́ láti dupò ààrẹ lẹ́gbẹ́ APC gẹ́gẹ́ báwọn ọmọdé náà ti lẹ́tọ̀ọ́ - Jandor
- Àjọ SERAP gbé Buhari lọ sílé ẹjọ́ lórí N106bn tí wọ́n ló d'àwátì láwọn ilé iṣẹ́ ìjọba
- Àwọn jàndùkú afẹ̀mí-ṣòfò ṣekúpa èèyàn 24 ní Kaduna àti Katsina lọ́jọ́ kan ṣoṣo
- Kí ló lè mú ìjọba pàṣẹ pé kí wọ́n ka gbogbo ẹranko igbó àti ẹja inú omi?
Oluwo Ifa ti Egba naa sọ pe idi ti Naijiria ṣe n koju oniruru iṣoro ni ẹka eto abo ni pe awọn eeyan ti kọ awọn oriṣa adayeba silẹ, wọn ko si tẹle awọn alakalalẹ Ifa.
Baoku sọ pe ti Naijiria ba fẹ lati yanju awọn iṣoro to n koju rẹ, o ni lati lọ bi ifa leere.
O ni "Ijọba ti sun awa ẹlẹsin ibilẹ ti si ẹgbẹ kan, wọn ko si mọ pe awa gan ni ọna abayọ si awọn isọro to n koju Naijiria lọwọ yii.
"Awọn ilana kan wa to rọ mọ ẹsin ibilẹ, ti a ba ṣe awọn nnkan to yẹ ki a ṣe gẹgẹ bi ilana ọhun ṣe gbe kalẹ ni, a ko ni maa koju awọn iṣoro to n dojukọ ilẹ wa lonii."
Oluwo Ifa ọhun wa ke si gomina dapo Abiodun ti ipinlẹ Ogun lati kede ayajọ ọjọ ọdun Iṣẹṣe naa, to jẹ ogunjọ, oṣu Kẹjọ ninu ọdun gẹgẹ bii ọjọ isinmi lẹnu iṣẹ ki awọn to n ṣe ọdun naa le ri aye lati ṣe etutu to yẹ.
O fi kun pe kii ṣe ifakokoṣofo ni ti awọn eeyan ba n ṣe ọdun Ifa.
Ẹwẹ, alaga ẹgbẹ Iṣẹṣe Parapọ ni Egba, Ifaniaki Amosun sọ pe ọdun Iṣẹṣe naa ni ọna kan gboogi lati mu irẹpọ wa laarin gbogbo awọn oniṣẹṣe.
Ifaniaki ṣalaye pe "Gbogbo ẹlẹsin lo maa n kopa ninu eto idibo ni Najiria, ṣugbọn lẹyin ti awọn oloṣelu ba ti wọle ibo tan ni wọn maa n ṣe idẹyẹsi awọn ẹlẹsin ibilẹ."
"Ọdọdun ni awọn gomina maa kede ayajọ ọjọ isinmi fun awọn ẹlẹsin Kristẹni atawọn Musulumi, ki lo de ti wọn fi maa n yọ awa ẹlẹsin abalaye sẹyin?"
"O ye ki wọn ya ọjọ silẹ fun awa ẹlẹsin ibilẹ naa lati maa ṣe awọn isin wa, a n fẹ ki gomina wa ati minista fun ọrọ aṣa bojuwo ọrọ naa."
Lara awọn to peju sibi ọdun Iṣẹṣe naa ni Baba Iṣẹṣe ti Egba, Ọjọgbọn Ayinde Salami; Ojubono ti Egba, Oloye Onifade Ogundelde atawọn lọbalọba.
- Bobrisky@30: Àpótí òní páálí láwọn àlejò yóò fí wọlé síbi àpéjẹ̀ Bobrisky
- Ìwà àrífin ni fífi Sultan ti Shuwa Arab jẹ ní Edo - Ìjọba ìpínlẹ̀ Edo
- Ẹ̀yin akọ̀ròyìn, ẹ má kọ ìròyìn tó lè dá wàhálá sílẹ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ìṣekúpani Modakeke- Ọlọ́pàá
- Taliban ti sọjí o, wo ohun tí wọ́n kìí ṣe tẹ́lẹ̀, tí wọ́n ń ṣe báyìí















