Bandits killings: Àwọn jàndùkú agbébọn gbẹ̀mí èèyàn 24 ní Kaduna àti Katsina lópin ọ̀sẹ̀

Awọn agbebọn

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Awọn janduku agbebọn afẹmi-ṣofo tun ṣọṣẹ lọjọ Aiku, ọjọ kejilelogun oṣu kẹjọ nipinlẹ Kaduna ati Katsina.

Lọjọ Abamẹta lawọn kọlọnbiti ẹda ọhun kọkọ yabo awujọ Duba ni ijọba ibilẹ Batsari nipinlẹ Katsina nibi ti wọn ti ṣekupa eeyan mejila.

Eeyan mejila mii tun dero ọrun labule Mado, ni ijọba ibilẹ Zangon Kataf nipinlẹ Kaduna lẹyin ti ija bẹ silẹ laarin awọn darandaran atawọn eeyan abule naa to fẹ gbẹsan.

Batsari nibi ti wọn ti pa eeyan mejila ni ipinlẹ Katsina jẹ ibode awọn janduku afẹmi-ṣofo ti n ṣọṣẹ lẹkun iwọ oorun ariwa Naijiria.

Awujọ Batsari tun pa aala pẹlu igbo Rugu to wa lara ijọba ibilẹ mẹwaa tawọn janduku yii maa n ṣe ikọlu si.

Alukoro ile iṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kaduna, Isa Gambo fidi rẹ mulẹ pe awọn janduku agbebọn to le lọdunrun yabo ijọba ibilẹ Zangon Kataf pẹlu oriṣiiriṣii ibọn ati ohun ija oloro ni bii ago mẹsan ku iṣẹju mẹẹdogun lalẹ ọjọ Abamẹta.

Àkọlé fídíò, Yoruba Nation: Mo faramọ́ àtúntò 'Restructuring' tí kò lọ́wọ́ ìṣèlú nínú- Oba Ahmed Adeku

Gambo ṣalaye pe awọn janduku ọhun da ibọn dolẹ kete ti wọn de abule Duba, lẹyin naa ni wọn bẹrẹ si ni jale ninu awọn ṣọọbu, ti wọn si tun ji awọn ẹran ọsin eeyan ilu naa.

Alukoro ile iṣẹ ọlọpaa ni eeyan mẹfa lo farapa yatọ si eeyan mejila to gbẹmi mi nibi iṣẹlẹ ọhun.

Àkọlé fídíò, Oba Ogboni Abalaye n fẹ́ kí wọ́n o má a fi ẹ̀sìn àbáláyé búra fún àwọn olóṣèlé Naijiria

O fidi rẹ mulẹ pe awọn ọmogun atawọn ọlọpaa ṣi n tẹsiwaju lori ati le awọn janduku ọhun kuro ni Kaduna.

Gambo ni awọn eeyan mẹfa to ṣeeṣe nibi iṣẹlẹ ọhun ti n gba itọju nile iwosan.

Àkọlé fídíò, Ọlatunji, akẹ́kọ̀ọ́gboyè 'graduate' tó ń ta àkàrà 'Ó ta lẹ́nu' nílùú Osogbo