Kano female vigilante: Wo àwọn obìnrin ''fijilanté" tí wọ́n ṣetán à ti kojú ẹnikẹ́ni ní Kano

Obinrin fijilante Kano

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ló máa ń sọ wí pé kò sí ohun tí ọkùnrin ń ṣe tí obìnrin pàápàá jùlọ lóde òní.

Ìgbàgbọ́ àwọn ènìyàn kan tẹ́lẹ̀ ni pé àwọn iṣẹ́ kan kìí ṣe ohun tí obìnrin le ṣe ṣùgbọ́n èyí ti ń yí padà lóde òní nítorí a ti ń rí obìnrin tó ń tún ọkọ̀ ṣe, obìnrin tó ń kanlé àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ à ti pe àìrìn jìnà làìrí abuké ọ̀kẹ́rẹ́.

Ní ìlú Kano, àwọn obìnrin kan ti ń ṣe bẹbẹ bí wọ́n ṣe darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ àwọn ọladẹ fìjilanté lójúnà à ti pọn kún ètò ààbò ní ìpínlẹ̀ náà.

Nígbà tó ń sọ ipa tí wọ́n ń kó sí ríri pé àdínkù bá ìwà ọ̀daràn ní ìpínlẹ̀ Kano, Aisha Abubakar, ọ̀kan lára àwọn obìnrin fijilanté náà ní àwọn kìí bẹ̀rù láti nawọ́ gán ẹnikẹ́ni tó bá tẹ òfin lójú mọ́lẹ̀.

Àkọlé fídíò, Oyetola, Aregbesola àti Tinubu ni ọ̀rọ̀ náà wa láàrin wọn

Aisha Abubakar ní ohun tó mú òun darapọ̀ mọ́ fijilanté ni láti kó ipa tirẹ̀ lórí mímú àdínkù bá ìwà ọ̀daràn àti pé àwọn obìnrin ní ipa tó lóòrìn tí wọ́n ń kó sí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ àwùjọ.

Ó ní iṣẹ́ àwọn dàbí ti àwọn ológun tí kò sí pé ọkùnrin tàbí obìnrin ló le ṣe iṣẹ́ kan, gbogbo àwọn ni àwọn jọ ní àfojúsùn kan náà.

Àkọlé fídíò, Igbe àyé Ọbáfẹ́mi Awólọ̀wọ́ nigba aye rẹ̀

Kini awọn akọni fijilante yii tun sọ?

Bákan náà ló ní àwọn kìí bẹ̀rù láti mú ọ̀daràn ìbáà ṣe ọkùnrin tàbí obìnrin ní wọ̀n ìgbà tí wọ́n bá ti hu ìwà ọ̀daràn, àti pé wọ́n máa ń bẹ̀rù àwọn nítorí ọ̀daràn máa ń bẹ̀rù ẹni tí tó bá jẹ́ agbófinró.

Àkọlé fídíò, Oja Odan nibi ti wọn ti dáná sún afurasi meji ti wọn ba ori eeyan lọwọ wọn

Ẹlòmíràn tí òun náà jẹ́ fijilanté obìnrin tó bá BBC Pidgin sọ̀rọ̀, Hadiza Tanko ní nítorí bí àwọn ọ̀dọ̀ ṣe ń ṣàmúlò egbògi olóró ló mú òun darapọ̀ mọ́ fijilanté.

Tanko ní ó máa ń rọrùn fún àwọn obìnrin láti ṣe ìwádìí lábẹ̀nú ju ọkùnrin lọ nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn máa ń finú tán obìnrin púpọ̀.

Àkọlé fídíò, Ìjẹ̀bú: Àgbàlàgbà ni mo máa ń ṣe nínú eré tẹ́lẹ̀

Ẹni kẹta wọn, Zuwaira Abdullahi ní ohun tó fún òun ní ìwúrí láti ṣiṣẹ́ òun bí iṣẹ́ ni àtìlẹyìn tí ọkọ̀ òun fún òun láti darapọ̀ mọ́ fijilanté.

Abdullahi ní ọjọ́ tí òun kò le gbàgbé lẹ́nu iṣẹ́ náà ni ọjọ́ tóun ká ọkùnrin kan mọ́ ilé àkọ́kù tó fẹ́ bá ọmọdébìnrin kan tó ń kiri oúnjẹ ní ìbálòpọ̀.

Àkọlé fídíò, Aeroplane House: Látọdún 1999 ni mo ti bẹ̀rẹ̀ kíkọ́ ilé yìí fún ìyàwó mi ọ̀wọ́n

Abdulahi ṣàlàyé pé ọmọdébìnrin náà ń bẹ̀rù à ti padà sílé nítorí ó ní ìyá òun máa na òun wí pé òun kò ta oúnjẹ tí òun kiri lọ tán.

"Ọkùnrin náà wá ṣèlérí fún un láti fun ní gbogbo oúnjẹ tó kiri owó tó bá gbà láti ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú òun, níbẹ̀ láti nawọ́ gan.

Àkọlé fídíò, Segun iberu

Nígbà tó ń sọ̀rọ̀, sgá àgbà fijilanté ní Kano, Shehu Rabiu ní ìdí tí àwọn fi dá ẹ̀ka ti àwọn obìnrin sílẹ̀ ni pé àwọn obìnrin ní ipa to pọ̀ láti kó sí mímú àdínkù bá ìwà ọ̀daràn láwùjọ.

Rabiu ní gbogbo ìdánilẹ́kọ̀ọ́ tó yẹ àti èyí tí wọ́n nílò láti ṣe iṣẹ́ wọn dójú àmì ni àwọn ti fún wọn pẹ̀lú èròńgbà pé ọ̀pọ̀ àwọn obìnrin yóò tún darapọ̀ mọ́ iṣẹ́ náà.

Àkọlé fídíò, 'Ǹkan tó jẹ́ kí iṣẹ́ ọ̀nà tèmi yàtọ̀ lágbàáyé ni ǹkan tí mò ń lò'

Fijilanté ní Nàìjíríà

Gẹ́gẹ́ bí onímọ̀ nípa ètò ààbò, Isa Hashidu ṣe wí, ó ti lé ni ogún ọdún tí wọ́n dá fijilanté sílẹ̀ láti máa dọdẹ àdúgbò tí wọ́n sì forúkọ lábẹ́ òfin.

Àkọlé fídíò, 'Ìyá Tíṣà lòdì sí kí n mutí, fagbó tàbí sìgá'

Àwọn ará àdúgbò tí wọ́n ń dọdẹ ló sábà máa ń jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ wọn.

Gbogbo ìpínlẹ̀ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ni wọ́n ní ọmọ ẹgbẹ́ sí.

Àkọlé fídíò, Kong Thong: Àwọn òbí máa ń súfèé kọrin tàbí hu láti pe ọmọ tó bá dàgbà

Bákan náà ni wọ́n ní ìbáṣepọ̀ tó dán mọ́nrán pẹ̀lú àjọ ọlọ́pàá láti dá ààbò bò àwọn ará ìlú.

Ènìyàn tó bá ti pé méjìdínlógún ló le darapọ̀ mọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí òfin wọn ṣe làá kalẹ̀.

Àkọlé fídíò, OAU student's death: O dun OAU pé Heritage kú, agbìyànjú láti gbé e délé ìwòsàn ṣùgbọ́n...