Jaigbade Alao, àgbà ọ̀jẹ̀ olórin dadakuàdà tó fiṣẹ́ orin sílẹ̀ ní Ilorin lẹ́ni ọgọ́fà ọdún

Oríṣun àwòrán, Others
Bi eeyan ba maa n fi ọkan ba orin dadakuada bọ ko ni jẹ ajoji si ti wọn ba darukọ Jaigbade Alao.
Sawawu kan naa ni Jaigbade wa pẹlu awọn olorin Dadakuada mii bi Odolaye Aremu, Aremu Ose, Iyabo Baluu, Omoeke Amao ati Iya Tamiwo.
Amọ ninu gbogbo wọn, ko si ẹni ti wọn da lọla pẹlu oye Oba Orin bi ti Jaigbade Alao.
- Àwọn ọba Yorùbá kan rèé tí wọ́n rọ̀ lóyè, tí ọba míràn jẹ lójú ayé wọn
- Kí ló fà ogun Ìjàyè àti ìṣubú Kurunmi, ìfẹ́ ìlú ni àbí orí kunkun?
- Duro Ladipọ, ìlúmọ̀ọ́ká òṣèré tíátà àti ọmọ àlúfà tí kò gbàgbé àṣà ìbílẹ̀
- Ìtàn ìgbésí ayé Oshodi, ọmọ Tápà léǹpe tó di akọni ní ìlú Eko
- Ìtàn Manigbagbe: Àwọn àjakalẹ-àrun to ti wáyé rí ṣáájú Coronavirus
- Wo àwọn gbajúmọ̀ òṣèré Yorùbá tí kìí ṣe ọmọ káàárọ̀ oòjíire
- Ǹjẹ́ o mọ àwọn òṣèré bí Oyin Adejọbi, Funmi Martins àtàwọn míì tó ti dágbére fáyé?
- Agbára ṣì wà lọ́wọ́ Boris Johnson bo tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ n fi iṣẹ́ sílẹ̀
Tani Jaigbade Alao?
Jaigbade Alao taa bi ni ilu Ilorin ti kede pe oun ti setan bayi lati fi isẹ orin kikọ silẹ lẹyin ọpọ ọdun.
O kede ọrọ yi ni aafin Oba ilu Ilorin, Emir Ibrahim Zulu Gambari laipẹ yi.
Bi ẹ ba salabapade fọnran fidio ibi to ti lọ kan saara si Emir, Jaigbade Alao sọ pe oun n palẹmọ ayẹyẹ ọjọ ibi ọgọfa ọdun oun ati pe asiko to lati fa isẹ orin le ọmọ oun Muhammad Jamiu lọwọ.
Ọtọ ni tọlu ọtọ ni tọlu wo, ninu awọn olorin ibilẹ Dadakuada, Alhaji Aminullahi Jaigbade Alao tan bi osupa to si da yatọ kedere.
Akọsilẹ wa pe o ti n ba isẹ orin bọ, ọjọ ti pẹ.
Ninu awọn Emir Ilorin, o kere tan,mẹrin ninu wọn ni Jaigbade kọrin fun bẹrẹ lati igba Emir Abdulkadir Suhaib Bawa (1920 -1959) titi to fi kan Emir toni Emir Ibrahim Zulukarnaini Gambari.
Dadakuada, iru orin wo ni à n pe bẹẹ?
Ilu Ilorin ni Dadakuada ti gbilẹ daadaa, ti o si fidi mulẹ gẹgẹ bi orin ibilẹ nibẹ.
Tonile talejo to nifẹ si orin yi lo jẹri pe o kun fun ọgbọn ati oye eleyi to papọ mọ asa Ilorin gẹgẹ bi ilu ti Islamuu fidi mulẹ.
Bawo ni orin Dadakuada ṣe bẹrẹ?
Ọjọgbọn Abdulrasheed Na'Allah ninu apilẹkọ rẹ salaye pe orisun orin dadakuada wa lati ibi Egungun ilẹ Yoruba.
Ijala, ọfọ pipa ati orin eebu jẹ apẹrẹ orin taa le ri ninu dadakuada.
Lode oni, ko fẹ ẹ si apẹrẹ orisun Egungunninu orin naa nitori bi awọn akọrin dadakuada ti se ti fi ọrọ ẹsin Islamuu se opo to mu orin wọn ro.
Kini yoo ṣẹlẹ lẹyin ifẹyinti Jaigbade Alao?
Bayi ti Jaigbade Alao wa pe ẹni ọgọfa ọdun o tọ ki a wo ipa to ko ninu orin ibilẹ yi ka si beere pe se awọn ti yoo sele de lẹrin rẹ ti wa bayi.
Ọpọ lo mọ orin dadakuada nipasẹ Jaigbade Alao.
Ninu orin rẹ, o mu iyipada ba dadakuada pẹlu bo se n yi awọn orisi orin mii pẹlu rẹ.
Baa se n ri Fuji, Waka ati Juju ninu dadakuada bẹẹ naa lo yi orin ẹmi naa sinu rẹ to si jẹ ki awọn eeyan nifẹ si orin dadakuada.
Se dadakuada ti wa de opin bayi ti Jaigbade fẹyinti nidi orin?
Idahun si ibeere yi jẹyọ lasiko to se afihan ọmọ rẹ Muhammad Jamiu fun Oba ilu Ilorin.
Arakunrin naa jẹwọ ara rẹ pẹlu orin nipa kiki Oba Ilorin to si fi han pe Jaigbade le ti fẹyinti nidi orin sugbọn awọn to n se'lede rẹ naa ko gbẹyin.
- Mọ̀ sí i nípa Oba Yesufu Asanike, Olubadan tí kìí fi ọ̀rọ̀ sí abẹ́ ahọ́n sọ kódà níwájú sọ́jà
- Ọdaràn làwọn tó ń pè fún ìdìbò dípò 'Restructuring' tí a n béèrè- Iba Gani Adams OPC
- A kò fi ẹbí Timothy sílẹ̀, à ń gbiyànjú pé kí wọ́n dá ẹjọ́ náà padà sí Osun dípò Abuja ni- Agbẹjọ́rò Adekilekun
- Ọ̀gá àgbà NSCDC dá àwọn ẹ̀ṣọ́ àjọ náà tó wà pẹ̀lú Shina Peller padà
- Ìjọba Tanzania fòfin de gbígbé ọmọ wá sí kíláàsì ìkẹ́kọ̀ọ́
- Èèyàn 26 kú nígbà tí wáyà iná já lé wọn lórí láàrin ọjà




















