Timothy Adegoke's court case: Kí ló dé tí agbẹjọ́rò mọ́lẹ́bí Timothy Adegoke kò ṣe farahàn nílé ẹjọ́ ní Abuja?

Timothy Adegoke

Oríṣun àwòrán, Others

Ki lo de ti agbẹjọro fun mọlebi Timothy Adegoke ko fi ara han nile ẹjọ ni ibeere ti ọpọ n beere bayii.

Arakunrin Gbade Adegoke ti o jẹ ẹgbọn fun oloogbe Timothy Adegoke, akẹkọọ fasiti Ọbafẹmi Awolọwọ ti wọn deede ri oku rẹ ni ayika ile itura ti o de si ninu ọṣu kọkanla, ọdun 2021 ti ke gbajare wi pe idile naa nilo awọn agbẹjọro agba ti o le ṣe iranlọwọ fun wọn lati ri idajọ ododo gba.

Bawo ni ọrọ ṣe jade?

Ninu fọran kan ti o lu sita lori itakun ayelukara l'Ọjọru ni Gbade ti fi igba ta wi pe igbẹjọ to yẹ ko waye lori awọn afurasi ti ọwọ ijọba tẹ ko kẹsẹjari nitori agbẹjọro to n ṣoju fun mọlẹbi naa ko fi ara han nile ẹjọ.

Arakunrin Gbade Adegoke ni, "Gbogbo iranlọwọ ti ẹ ba le ṣe fun wa, a fẹ agbẹjọro. Agbẹjọrọ agba sini a fẹ.

Àkọlé fídíò, OLota

O le jẹ meji, mẹta, mẹrin tabi ju bẹẹ lọ. Ẹ jọọ ko si ẹni ti mo fẹ lọ fun ni abọ nile mọ. Nnkan ti mo ba sọ nibi ni abẹ ge. Maa sọ fun wọn nile wi pe bayii ni".

Arakunrin Gbade Adegoke kẹsi ijọba ipinlẹ Ọyọ ati ijọba orilẹede Naijiria lati dide fun iranlọwọ nitori ko ni daa ki ọrọ naa lọ bẹẹ lai si idajọ ododo.

Awọn ẹsun wo ni wọn ka kalẹ bayii?

Lara awọn ẹsun ti ẹgbọn oloogbe naa fi kan an ni pe awọn eeyan kan ti n dun kukulaja mọ oun lori ọrọ naa.

Kí ló dé tí agbẹjọ́rò mọ́lẹ́bí Timothy Adegoke kò ṣe farahàn nílé ẹjọ́ ní Abuja?

Timothy Adegoke

O ni ọkan ninu awọn eeyan naa ti o lepa oun wa si ilu Eruwa tẹlẹri ni oun tun dede pade nile ejo nilu l'Abuja, ti ẹni naa si ṣe ileri lati fi okun de oun bi oun ba gbiyanju lati sun ilu Abuja mọju.

Bakan naa ni Arakunrin Gbade fi kun ọrọ rẹ pe ninu ewu ni oun wa bayii, bẹẹ sini oun ni ipaya lori aabo ẹmi.

Àkọlé fídíò, Ipaniyan Ogun

Bawo ni ọrọ ṣe kan Agbejọro?

Iroyin ti o tun tẹlẹ igbe ti ẹgbọn oloogbe fi ta ni pe awọn agbẹjọro to yẹ ki o ṣoju idile wọn ko fi ara han nile ẹjọ ti wọn ti fi oju awọn afurasi han nilu Abuja.

Eyii lo mu ki a kan si ọkan lara awọn agbẹjọro fun mọlẹbi Adegoke, Amofin Naheem Adekilekun ki a le fi idi otitọ mulẹ.

Kini Agbẹjọrọ naa sọ fun BBC Yoruba?

Adekilekun ṣe alaye fun akọroyin wa pe ipinlẹ Ọṣun ti wọn ti ri oku oloogbe Timothy Adegoke lo yẹ ki igbẹjọ ti waye gẹgẹ bi nnkan ti ofin sọ.

O ni igbiyanju lati mu ki wọn gbe ẹjọ naa pada wa si ipinlẹ Ọṣun ni awọn agbẹjọro fun mọlẹbi Adegoke n ba kiri.

Eyii lo si faa ti wọn ko ṣe fi ara han nibi igbẹjọ akọkọ to waye nilu Abuja.

Àkọlé fídíò, Timothy Adegoke

Agbẹjọro naa tẹsiwaju wi pe aifi ara han agbẹjọro fun mọlẹbi Adegoke nile ẹjọ to n bẹ nilu Abuja ko ṣe okunfa idiwọ kankan bo ti n wu ki o mọ.

O ni nitori pe "ọrọ ẹjọ ti o ba ti ni ọwọ ẹsun iwa ọdaran ninu bayẹn, ijọba ati awọn afẹsunkan ni o kan ju. Ohun ti mọlẹbi le ṣe ko ju ki mọlẹbi jẹ bi i ẹlẹri fun ijọba lọ.

Nitori naa, ailọ wa lanaa ko ba nnkan kan jẹ".

Àkọlé fídíò, Tọktaya afọju ti Eledua tun fi ibeji ta lọrẹ

Adekilekun fi idi ọrọ mulẹ pe oun ati awọn akẹgbẹ oun ko ti i yọwọ ninu ẹjọ naa, bẹẹ sini ẹni kankan ko dun kukulaja mọ wọn lati jawọ ninu ẹ.

O ni bi ọrọ ṣe ye ẹgbọn oloogbe mọ, lo mu ki o pariwo sita lori itakun ayelukara.

O fi kun ọrọ rẹ wi pe awọn yoo fi ara han nibi igbẹjọ mii ti yoo waye.

Àkọlé fídíò, Omi Daji: Odò tó dédé sàn jáde tí kìí gbẹ tòjò tẹ̀ẹ̀rùn, wọn kìí pa tàbí jẹ ẹja inú rẹ̀