Oodua Peoples Congress: Ọdaràn làwọn tó ń pè fún ìdìbò dípò 'Restructuring' tí a n béèrè- Iba Gani Adams

Oríṣun àwòrán, @Iba Gani Adams
Aarẹ Ọna Kakanfo ilẹ Yoruba Gani Adams ti kesi aarẹ Muhammadu Buari lati ri pe o fi iwe ofin miran parọ ti 1999 to wa nilẹ saaju ki idibo ọdun 2023 to waye.
Adari ati agbaọjẹ ilẹ Yoruba yi ni ki aarẹ Buhari mu atunto ba orileede Naijiria ati pe nkan to seese ni ti aarẹ ba fi ọkan si.
Lasiko to n ba awọn akọroyin sọrọ ni Ile Ife nibi asekagba ajọdun Oduduwa lọjọ Aje ni o ti fi ọrọ yi lede.
- Mi ò kọ Atiku Abubakar nítorí pé o fẹ́ ìyàwó mìíràn- Jennifer Douglas Abubakar
- China sinmi lórí yíyá Nàìjíríà lówó, èyí lè fà ìdádúró lórí iṣẹ́ rélùwé
- Ìdìtẹ̀gbàjọba tó fẹ́ wáyé ní orílẹ̀-èdè Guinea Bissau, wo ohun tí a lè fìdíẹ̀ múlẹ̀ nípa rẹ̀
- Jide Kosoko, Otunba Dodoede n selédè lẹ́yìn Tafa Oloyede tó kú
Kini Iba Gani Adams tun so nibẹ?
Iba Gani Adams sọ pe ẹnikẹni to ba n pe fun idio labẹ eto ijọba yi,ọdaran lo yẹ ki wọn pe onitọhun.
O sọ pe ''atunse iwe ofin Naijria gbọdọ waye saaju idibo ọdun 2023.Mi o ni sọ pe ki idibo ma waye ni 2023 sugbọn o se pataki ti a ba fẹ tẹsiwaju gẹgẹ bi orileede, ki a se atunto si agbegbe''
''Bi a ko ba se eleyi, mo nigbagbọ pe ẹnikẹni ti a ba yan sipo, ko ni ri nkankan se labẹ eto taa n tẹle yi.Bi a ba dibo wọle fun , yoo maa sojo lati fọwọ kan iwe ofin.Buhari n palẹmọ bayii, asiko diẹ lo wa fun lati tun eto yi se kuro nibi to wa bayii.''
Gani Adams wa kesi awọn ile asofin ati alẹnulọrọ lati mu iyipada ba iwe ofin si ti ẹda ọdun 1960 ati 1963 ki Naijiria baa le ni ilọsiwaju.
Lakotan, Gani Adams kesi Ooni Ile Ife Oba Adeyeye Ogunwusi pe ki o ba awọn Gomina ipinlẹ kaarọ o jiire lati ya ọjọ sọtọ fayajọ ayẹyẹ Oduduwa to jẹ babanla awọn Yoruba.
- Àjọ SERAP gbé Ààrẹ Buhari lọ sílé ẹjọ́ nítorì kò wádìí N3B tó pòórá níléèṣẹ̀ ètò ẹ̀náwó
- Wo àwọn ìgbéyàwó tí ayé pariwo wọ́n lọ́dún tó lọ
- Àwọn nǹkan mẹ́ta tí a kò tíì mọ̀ nípa Covid-19 lẹ́yìn tí àrùn náà bẹ́ sílẹ̀ rèé
- 'A kò le gba ẹlẹ́wọ̀n kankan wọlé mọ́, kò sí òunjẹ tá a fẹ́ fún wọn'
- Musulumi àti Kristẹni lo ṣe àdúrà níbi ètò ìsìnkú Timothy Adegoke lónìí
- Òkú kú ní ẹ̀ẹ̀kejì nígbà tí òkú 400 jóná ráúráú ní mọ́ṣúárì, ẹbí bú sẹ́kún lẹ́ẹ̀kejì















