Tafa Oloyede: Bí ìsìnkú John Adewumi, àgbà òṣèré tíátà yóò ṣe lọ rèé

Tafa Oloyede

Oríṣun àwòrán, @Tafa Oloyede

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Gbajúgbajà òṣèré John Adewumi ti ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Tafa Oleyede tó jáde láyé lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun, kìíní oṣù kejì yóò káà ilẹ̀ sùn lọ́jọ́ Ẹti, ọjọ́ kọkànlá oṣù kejì.

Gómìnà ẹgbẹ́ TAMPAN ní ìpínlẹ̀ Osun, Alhaji Moruf Lawal lo sọ èyí nílùú Osogbo.

Lawal ní àwọn tí parí gbogbo ètò pẹ̀lú àwọn mọ̀lẹ́bí olóògbé náà nipa bi isinku rẹ yoo se lọ.

Ó ní lọ́jọ́bọ, ọjọ́ kẹwàá osu keji ọdun 2022 ni ẹgbẹ́ àwọn osere tiata yóò ṣe ayẹyẹ idagbere fun, ta tun mọ si "Artist Day".

Àkọlé fídíò, Jejere

Ile rẹ to wa ní ìlú abinibi Tafa Oloyede, Ẹdẹ ni eto naa yoo ti maa waye bẹrẹ lati aago méjì ọ̀sán sí aago mẹ́fà ìrọ̀lẹ́.

Bẹ́ẹ̀ náà ló ní alẹ́ àìsùn onígbàgbọ́ yóò wáyé lọ́jọ́bọ bákan náà, kí olóògbé tó máa lọ sinmi láyà olùgbàlà lọ́jọ́ Ẹtì, ọjọ kọkànlá.

Àwọn àgbà òṣere n ṣe idaro Tafa Oloyede to re ibi agba n re yii.

Gbajúgbajà òṣèré tíátà nì, John Adewumi tí ọ̀pọ̀ mọ̀ sí Tafa Oloyede dágbére fáyé

Jide Kosoko, Otunba Dodoede n selédè lẹ́yìn Tafa Oloyede tó kú

Ni kete ti iroyin iku oloogbe John Adewumi ni awọn agba oṣere bii Adebayo Bello ti ọpọ n pe ni Oga Bello ti n ṣe idaro rẹ .

Skip Facebook post, 1

Content is not available

View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.

End of Facebook post, 1

Awon mii tun ni Otunba Adekunle Abolade Dodoede to mẹnuba awọn ere Oloogbe Tafa to gbadun bii Ayanmọ Ekuro ọlọja, Orogun, Akanji Oniposi ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Skip Facebook post, 2

Content is not available

View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.

End of Facebook post, 2

Ikú dóró: Gbajúgbajà òṣèré tíátà Tafa Oloyede dágbére fáyé

Kò sí bó ti wù ká gbajúmọ̀ tó nílè ayé tàbí kí a là kàkà tó, ọjọ́ ọjọ́ kan la ó ṣe dúnìyàn lódìgbà.

Gbajúgbajà òṣèré tíátà, John Adewumi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn mọ̀ sí Tafa Oloyede ti dágbére fáyé.

Tafa Oloyede

Oríṣun àwòrán, @Tafa Oloyede

Lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun ni Tafa Oloyede mí mímí ìkẹyìn ní ilé rẹ̀ tó wà ní Arowomole, Osogbo, ìpínlẹ̀ Osun, lẹ́yìn àìsàn ráńpẹ́.

Oloyede, tó di gbajúgbajà òṣèré lẹ́yìn tó kópa nínú eré Akanji Oniposi, fi ìyàwó àti àwọn ọmọ sáyé lọ.

Ta ni Tafa Oloyede?

John Adewumi ni orúkọ tí ìyá àti bàbá rẹ̀ sọ ṣùgbọ́n orúkọ ìnagijẹ rẹ̀ ni Tafa Oloyede.

Ní ọjọ́ kọkàndínlógún, oṣù kọkànlá ọdún 1952 ni wọ́n bi, tó sì bẹ̀rẹ̀ eré tíátà lọ́dún 1974.

Àkọlé fídíò, Ipaniyan Ogun

Ọmọ bíbí ìlú Ẹdẹ ní ìpínlẹ̀ Osun ni, tó sì lọ sí ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti girama ní ìpínlẹ̀ Osun.

Ó ti kópa nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ eré bíi Jayesinmi, Ayanmo, Ekuro Oloja, Orogun, Akanji Oniposi àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.