Guinea-Bissau 'coup attempt': Ìdìtẹ̀gbàjọba tó fẹ́ wáyé ní orílẹ̀-èdè Guinea Bissau, wo ohun tí a lè fìdíẹ̀ múlẹ̀ nípa rẹ̀

Guinea Bissau

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò bá ìṣẹ̀lẹ̀ ìdìtẹ̀gbàjọba tó fìdí rẹmi ní Guinea-Bissau lọ - Ààrẹ Embaló

Ààrẹ Embaló ní ọ̀pọ̀ ènìyàn dágbére fáyé níbi ìdìtẹ̀gbàjọba tó fìdí rẹmi ní Guinea-Bissau

Ààrẹ Umaro Cissoko Embaló ti ní ìdìtẹ̀gbàjọba tó fìdí rẹmi ní orílẹ̀ èdè Guinea-Bissau ṣokùnfà kí ọ̀pọ̀ àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò.

Kini Aarẹ Embalo kọkọ fi sita?

Ààrẹ Embaló ṣàlàyé pé àwọn ṣe ohun gbogbo tó wà ní ìkáwọ àwọn láti ri dájú pé ìdìgbàjọba náà kò wáyé bí ó ṣe ní àbùkù ní sí ètò ìjọba àwaarawa.

Àkọlé fídíò, Ipaniyan Ogun

Lọ́jọ́ Ìṣẹ́gún ni ìró ìbọn bẹ̀rẹ̀ sí ní dún ní ẹ̀gbẹ́ ilé Ààrẹ lásìkò tó ń ṣèpàdé pẹ̀lú àwọn ìgbìmọ̀ aláṣẹ rẹ̀.

Ìròyìn ní àwọn ológun fi Ààrẹ àti àwọn Mínísítà rẹ̀ sí àhámọ́ nígbà tí àwọn kan yabo ilé Ààrẹ lásìkò tí Ààrẹ Embaló ń ṣèpàdé pẹ̀lú Mínísítà Nuno Gomes Nabiam.

Àkọlé fídíò, Timothy Adegoke

Ẹ̀ṣọ́ aláàbò kan tí kò fẹ́ kí a dárúkọ òun tó bá ikọ̀ ìròyìn BBC sọ̀rọ̀ ní àwọn agbébọn náà pa ọlọ́pàá kan nígbà tí wọ́n dàbọn bolẹ̀ lásìkò tí wọ́n ṣe ìkọlù sí ẹ̀bá ilé Ààrẹ.

Àkọlé fídíò, Ogun King Killing: Baálẹ̀ Agodo ní ààrin Ẹ̀gẹ́ ni òun sùn mọ́jú, tí òun kò sì rí aya, ọmọ

Àwọn adarí ìwọ̀ oòrùn ẹkùn Adúláwọ̀ ti bu ẹnu àtẹ́ lu ìdìtẹ̀gbàjọba tó ń wáyé tí wọ́n sì ní kí àwọn ológun padà sí bárékè.

Àkọlé fídíò, Akàwégboyè alákàrà