NDLEA mú ìyá ẹni ọdún 80 àti ọmọ-ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú onírúurú oògùn olóró l'Ondo

Oríṣun àwòrán, @ndlea_nigeria
Iya ẹni ọgọrin ọdun kan, ọmọ-ọmọ rẹ to jẹ ẹni ọmọ mejidinlogun atawọn eyan miran ti ko si gbaga ajọ to n gbogun ti egboogi oloro ni Naijiria, NDLEA, lori ẹsun pe n wọn ta oogun oloro.
Lara awọn egboogi oloro ti NDLEA ka mọ wọn lọwọ ni kokeni, heroin, methamphetamine, tramadol, swinol, colorado ati skuchies.
Ninu atẹjade kan ti agbẹnusọ NDLEA, Femi Babafemi fi lede, o ni ọwọ tẹ awọn afurasi naa lẹyin oniruru ọfintoto ti wọn ṣe, ati lẹyin ti awọn eeyan ilu kan ta awọn lolobo.
O fi kun pe iwọn egboogi oloro ti wọn ka mọ awọn afurasi naa lọwọ le ni kilo méjìléláàdọ́wàá (192kg).
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Ọwọ tẹ mama agba to wa lara awọn afurasi ọhun ti orukọ rẹ n jẹ Funmilayo Adebayo ni nnkan bii aago mẹfa abọ aarọ lagbegbe Adeyemi, to wa ni ijọba ibilẹ ila oorun Akure.
Lọjọ kan naa ni wọn fi ṣikun ofi mu afurasi miran ti orukọ rẹ n jẹ Tessy Mathew nigab ti wọ kọlu ile irtura Rate to wa niluu Akure kan naa.
Lẹyin naa ni awọn ọtẹlẹmuyẹ NDLEA tun mu afurasi miran, Blessing Adesida, ni agbegbe Oshinlẹ to wa ni ijọba ibilẹ Guusu Akure.
Nigba ti wọn n fi ọrọ wa iya agba ati ọmọ-ọmọ rẹ naa wo, awọn mejeji sọ pe awọn ko mọ pe òwò oogun oloro ti wọn n ṣe ko ba ofin mu.
Bakan naa ni wọn ni awọn ko mọ pe oogun naa le ba aye awọn eeyan jẹ.
- Kí ní Desmond Elliot ṣe fáwọn ọ̀dọ́ tí orúkọ rẹ̀ kò wọ́n lori ayelujara?
- Wo bí Rev'd Father Ejike Mbaka ṣe padà sílé lẹ́yìn tó 'di àwátì' fún ọjọ́ méjì
- Ẹ̀wọ̀n gbére tàbí ọlọ́dún mẹ́ta, méje, àtàwọn ìjìyà tó ṣééṣe kí Bàbá Ijeṣa jẹ rèé - Ìjọba ìpínlẹ̀ eko
- Nǹkan pàtàkì mẹ́wàá tó yẹ kí o mọ̀ nípa Salawa Abeni bí ó ṣe pé ọgọ́ta ọdún.
Bo tilẹ jẹ pe wọn ni awọn mọ pe wọn ko si gbaga ọlọpaa nitori awọn oogun oloro naa, wọn gba awọn araalu nimọra lati ma tọwọ bọ irufẹ owo bẹẹ.
Ẹwẹ, adari ajọ NDLEA, ọgagun Mohamed Buba Marwa ti ke si ọga agba ajọ naa nipinlẹ Ondo lati ṣawari awọn afurasi to ku ti wọn ti na papa bora.
- Àfinra! Amotekun lé àwọn Fulani 137 tó gba inú igbó ìjọba lọ́nà àìtọ́ kúrò l'Ondo
- Ikú tó fẹ́ pa Opeyemi Ayeola ṣí i ní fìlà, ló bá ń kọrin ẹ fọ̀rọ̀ mi kọ́gbọ́n
- Eré orí ìtàgé kọ́ ni pé Baba Ijesha ń tẹ ọmọ lára, ẹ yé gbè sẹ́yìn mi lọ́nà àìtọ́ - Yomi Fabiyi
- Ìjínigbé àti ìdigunjalè kò sí ní ìkáwọ́ ìjọba àpapọ̀ - Lai Mohammed














