Fulani herdsmen: A lé wọn kúrò l'Ondo nítorí wọn kò lè ṣàlàyé ohun tí wọ́n wá ṣe - Amotekun

Oríṣun àwòrán, @OndoFirstBorn
Ikọ Amọtẹkun ipinlẹ Ondo ti le awọn Fulani bi i mẹtadinlogoje kuro ninu igbo ti wọn gba lọna aitọ nipinlẹ naa, ti wọn si da olukuluku pada si ipinlẹ to ti wa
Inu Igbo Elegbeka ni opopona marosẹ Benin si Owo ni wọn ti ko wọn.
Adari awọn Amọtẹkun nipinlẹ Ondo Adetunji Adeleye lo fidi ọrọ yii mulẹ.
- Ẹ̀wọ̀n gbére tàbí ọlọ́dún mẹ́ta, méje, àtàwọn ìjìyà tó ṣééṣe kí Bàbá Ijeṣa jẹ rèé - Ìjọba ìpínlẹ̀ eko
- Mo bẹ Baba Ijesha wò l‘àhámọ́, ẹ́ gbọ́ wirínwirìn ọ̀rọ̀ nílé ẹjọ́ - Yomi Fabiyi
- Agbébọn tú alápatà mẹ́ta tí wọ́n jí gbé sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n gba ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ owó
- Ayé ń pè wá ní 'Yeyebrity' torí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha, nǹkan bà wá lágbo tíátà Yoruba"
O ni o fẹ si awọn leti pe awon kan ti gba inu Igbo ìjọba ni Elegbeka, lẹba Ifọn, nijọba ibilẹ Ose ni ipinlẹ naa, eyii si lo mu awọn gbe igbesẹ.
Adeleye fi kun pe awọn ko awọn eniyan naa wa si olu ile iṣẹ Amọtẹkun niluu Akure lati fi ọrọ wa wọn lẹnuwo, ọpọ wọn lo sọ pe awọn wa lati iha ariwa Naijiria sugbọn wọn ko le sọ pato nnkan ti wọn wa ṣe ni Ipinlẹ Ondo.
Gẹgẹ bi Adeleye ṣe sọ, o dabi ẹni pe awọn kan n padi apo pọ mọ awọn ajoji naa lati maa gbe inu Igbo ọhun lọna aitọ
O ni awọn ti da gbogbo awọn to wọle lọna aitọ naa pada si ibi ti wọn ti wa.
Laipẹ yii ni awọn ọmọ ikọ Amọtẹkun yii kan naa sin awọn mejilelogoji kan lati Kano ati Jigawa jade kuro ni ipinlẹ Ondo, lẹyin ti wọn ri wọn ni ilu Okitipupa.
Ikọ Amọtẹkun Ondo wa fi gbogbo awọn eniyan ipinlẹ lọkan balẹ pe aabo to daju wa fun gbogbo wọn ati nkan ini wọn.
- Kí ni àwọn Mùsùlùmí máa ń ṣe ní alẹ́ ọjọ́ 10 tó gbẹ̀yìn àwẹ̀ Ramadan?
- Haram ni kí èèyàn máa san owó ìtúsílẹ̀ fún àwọn ajínigbé - Sheikh Ibrahim Maqari
- Kí ni yóò ṣẹlẹ̀ lónìí láàrin ìjọba ìpínlẹ̀ Kaduna àtàwọn tó jí akẹ́kọ̀ọ́ fásitì Greenfield gbé?
- Microsoft gbé ìgbésẹ̀ láti pèsè iṣẹ́ 27,000 fún àwọn ọmọ Naijiria
Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?
Ìdí tí a fi lé àwọn Fulani 42 tó ya bo agbègbè Okitipupa padà sí ìpínlẹ̀ wọn - Ìjọba ìpínlẹ̀ Ondo

Oríṣun àwòrán, Rotimi Akeredolu Aketi
Ijọba ipinlẹ Ondo ti ṣalaye idi to fi da awọn ọkunrin mejilelogoji to jẹ ara oke ọya pada si ipinlẹ wọn.
Nibi ipade awọn akọroyin kan to waye niluu Akure ni adari ikọ Amotekun ipinlẹ naa, Adetunji Adeleye ti sọ pe awọn eeyan naa le ṣakoba fun eto abo ipinlẹ ọhun lo jẹ ki wọn le wọn kuro ni ipinlẹ naa.
Ṣaaju ni awọn eeyan agbegbe Okitipupa ti kọkọ ke gbajare si ijọba pe awọn gende ọhun to jẹ Fulani ya bo agbegbe wọn, eyi to da ibẹrubojo sọkan awọn araalu.
- Báyìí ni Ọlọ́pàá ṣe mú ayédèrú agbanisíṣẹ́ tó fipá bá Iniobong tó ń wá iṣẹ́ lòpọ̀ tó tún pa á
- Ọjọ́ mẹta péré lo ní báyìí láti ṣe àyẹ̀wò Covid19 ṣáájú ìrìnàjò wá sí Nàìjíríà!
- Kò sí àwáwí fún ìwà Baba Ijesha àmọ... -Yomi Fabiyi
- Bola Tinubu: Ọlọrun kò ní gbà kí Naijiria tún la ogun abẹ́lé míràn kọjá
- Tíṣà mu ọtí yó ló bá kó àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ọmọdé lọ ilé ijó oníhòhò
Ni kete ti awọn oṣiṣẹ ikọ Amotekun gbọ pe awọn Fulani kan ti gunlẹ si agbegbe Okitipupa ni wọn tẹkọ lọ si ilu naa.
Lẹyin ti wọn fi pampẹ ofin mu wọn tan ni wọn ko wọn sinu ọkọ akero ti wọn si gbe wọn lọ si ẹyin ibode ipinlẹ Ondo, ti wọn si ni ki wọn pada si ipinlẹ wọn.

Oríṣun àwòrán, Rotimi Akeredolu Aketi
Nigba to n ba awọn akọroyi sọrọ, Adeleye ni awọn Fulani naa sọ pe ileeṣẹ kan ti kii ṣe ti ijọba ni awọn n ba ṣiṣẹ, ajọ naa lo si ko awọn wa.
O ni "Lati bii ọjọ mẹta sẹyin ni a ti n gbọ pe awọn Fulani n ya bo ipinlẹ Ondo, iwadii wa si fi han pe agbegbe Okitipupa ni wọn n gbà wọle, idi ree ti a fi ṣe ọfintoto wọn ti a si ri pe iwaju baraki awọn ologun ni wọn korajọ si."
"Nigba ti a ṣe ifọrọwanilẹnuwo fun wọn, a ri pe wọn ko le ṣalaye ohun pato ti wọn wa ṣe ni ipinlẹ Ondo, pupọ ninu wọn si jẹ Fulani lati ipinlẹ Kano ati Jigawa."
- Bí àwọn gbajúmọ̀ ṣe pín rèé lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Èèmọ̀ wọ̀lú! Àwọn jàndùkú agbébọn pa kọmíṣọ́nnà àti ọlọ́pàá, wọ́n dáná sun àgọ́ ọlọ́pàá
- Kò sí ẹ̀rí tó dájú tí a lè lò láti yọ Pantami kúró n'íjọba Buhari- Ilé aṣòfin l'Abuja
- Wo ìdí tí ìjọba Naijiria ṣe fòfin de gbogbo arìnrìnàjò láti India, Brazil àti Turkey
- Orí yọ ẹ́ o Baba Ijesha tí mi ò rí fídíò èpè tí wọ́n ní ò ń ṣẹ́, ǹkan tí mi ò bá ṣe fún ẹ... - Iyabo Ojo
Adeleye tẹsiwaju pe "Wọn ko le ṣalaye ohun ti wọn wa ṣe ni ipinlẹ Ondo ati bi wọn ṣe de ipinlẹ Ondo gan, nigba to ya wọn ni idanilẹkọọ ni awọn wa ṣe ṣugbọn wọn ko le ṣalaye ileeṣẹ to n ṣagbatẹru idanilẹkọọ ọhun."
Adari ikọ Maotekun naa tẹsiwaju pe ewu n bẹ loko longẹ ipinlẹ Ondo ti wọn ba fi wọn silẹ, eredi ree ti wọn fi da awọn eeyan naa pada si ipinlẹ wọn.
Lẹyin naa lo ṣeleri pe awọn ileeṣẹ eto abo ipinlẹ ọhun yoo tẹsiwaju lati maa daabo bo awọn eeyan ipinlẹ naa.
- Buhari, wá nǹkan ṣe sí ètò àbò tó mẹ́hẹ ní Naijiria kó tó pẹ́ jù - Alaafin, Ooni
- Àsìkò ti tó kí wọ́n yọ Buhari lórí oyè kí àlááfíà lè padà sí Naijiria - PFN, Kukah, Ighodalo
- 'Senior' Bukky Black, ìtìjú ńlá lẹ jẹ́ fún ìran obìnrin àti ìyá- Iyabo Ojo
- Ọlọ́run Ọba ti pa ẹ̀gàn mi rẹ́, a bímọ l'Amẹrika - Lizzy Anjorin
















