Yoruba people: A ǹ fẹ̀ kí gbogbo ìpínlẹ̀ Yoruba ní Naijiria di ọ̀kan ṣoṣo - Ẹgbẹ́ YYSA

Oríṣun àwòrán, YYSA
Lọna ati jẹ ki gbogbo ọmọ Yoruba di ọkan ṣoṣo kaakiri ilẹ Naijiria, ẹgbẹ awọn ọdọ ilẹ Yoruba, Yoruba Youth Socio-cultural Association, YYSA, ti sọ pe ki gbogbo ipinlẹ Yoruba ni Naijiria di ọkan ṣoṣo.
Ninu atẹjade kan ti awọn alaga ẹgbẹ ọhun ni guusu iwọ-oorun Naijiria fọwọ si ni wọn fi ọrọ naa lede.
Atẹjade ọhun ni "Awa ẹgbẹ Yoruba Youth Socio-cultural Association n pe fun iṣọkan ati isopọ awọn ipinlẹ Yoruba ni Naijiria ki a le di ẹya ti ko ni ṣe fọwọ rọ ṣeyin kaakiri agbaye."
- Àwọn ohun mẹ́rin tó yẹ kí ẹ ko mọ nípa Ramoni Igbalode tí gbogbo ayé ń pè ní Hushpuppi
- Ikọ̀ ìjọba Ọ̀yọ́ dé lásìkò tí kò yẹ ni wọn kò ṣe wọlé - Ẹ̀bí Ajimobi fèsì
- Ọ̀pọ̀ èèyàn tí kò yin Ajimobi lojú ayé, tó ń yìn-ín lẹ́yìn ikú, yóò jẹ ìyà - Oníwáàsí
- Mo ti bá ọmọ ọwọ́ mẹ́ta lòpọ̀ sẹ́yìn, ọmọ oṣù mẹ́ta ló ṣìkẹrin - Afurasí jẹ́wọ́
Ẹgbẹ naa rọ gbogbo gomina ilẹ Yoruba lati fọwọ sowọpọ gbe awọn ileeṣẹ to wa labẹ Oodua Investment ga fun idagbasoke ẹya Yoruba.
Bakan naa ni wọn tun kesi gbogbo gomina to n ṣakoso awọn ipinlẹ guusu iwọ-oorun Naijiria lati kan si awọn akẹgbẹ wọn ni Kwara, Kogi ati Edo lati fimọ ṣọkan nitori ọpọ ọmọ Yoruba lo wa lati awọn ipinlẹ naa.
- Kanye West, akọrin tàkasúfèé fẹ́ ẹ̀ kojú Trump nínú ìdìbò ààrẹ l‘Amẹrika
- Akeredolu, tó ò bá fa àkóso Ondo lé mi lọ́wọ́ láàrin ọjọ́ 21, o tàpá sófin - Igbákejì gómìnà
- Ọ̀pọ̀ ìgbà ní Hushpuppi àtàwọn èèkàn PDP ti ya fọ́tò ní Dubai, EFCC ẹ wádìí wọn - APC ń lọgun
- Ènìyàn 603 ni èsì àyẹ̀wò fihàn pé ó tún ti ní ààrùn Coronavirus ní Nàìjíríà
Ẹgbẹ YYSA jẹ ọkan gboogi lara awọn ẹgbẹ ọmọ Oodua to n pe fun iṣọkan ati idagbasoke ilẹ Yoruba.
Afojusun ẹgbẹ naa ni lati jẹ ki gbogbo ẹya Yoruba jẹ ọkan ni Naijiria, nilẹ Afrika, ati lawọn ilẹ miran lagbaye bii Caribbean ati Guusu ilẹ Amẹrika.








