Ekiti APC Primary: Ìdìbò láti yan olùdíje APC fún ipò gómìnà l'Ekiti ń parí lọ láwọn wọ́ọ̀dù kan

Idibo ti pari lawọn wọọdu kan ti awọn miran si ti n mura ati pari tiwọn lawọn Ibudo idibo wọọdu mẹtadinlọgọsan ti eto idibo ati yan oludije sipo gomina lẹgbẹ oṣelu APC ti n waye nipinlẹ Ekiti.
Bi o tilẹ jẹ pe awon oludije mẹfa kede lolu ileeṣẹ ẹgbẹ oṣelu APC nilu Ado Ekiti pe awọn ko lọwọ si eto naa mọ, afi ki awọn adari ẹgbẹ oṣelu naa wọgile idibo ọhun.
Oludije ti awuyewuye n mi dugbẹdugbẹ lori rẹ, Ọgbẹni Bamiji ni awọn ẹsun ti awọn oludije yooku n gbe dide ṣe ajeji si oun nitoripe oun ko gbọ pe ẹnikẹni ninu wọn tako eto yiyan oludije ẹgbẹ oselu naa.
- Ilé aṣòfin n rẹkẹ, Boris Johnson takú, tá ní yóò bóri lórí awuyewuye ''party'' ọjọ́ ìbí?
- Wo ohun tí ìjọba Oyo ṣe fún ẹni tí ọlọ́pàá SARS lù fọ́ lójú lẹ́yìn àbọ̀ ìgbìmọ̀ EndSARS
- Ẹ̀yín àgbà Yorùbá, ẹ dìde yanjú aáwọ̀ òṣèlú láàrin Tinubu àti Osinbajo, bíbẹ̀ẹ́kọ́... - Ajulo
- Erin tẹ arìnrìn-àjò pá níbi tó ti ń ṣẹ̀yọ́
- Michael Jackson, ọkùnrin tó sọ ara rẹ̀ di obìnrin kó sí pańpẹ́ EFCC
Amoṣa o ni inu oun dun si bi eto naa ṣe n lọ, gbogbo ikunsinu awọn oludije yoku ni wọn yoo si yanju gẹgẹ bi ọrọ mọlẹbi laarin agbo ẹgbẹ oṣelu naa.
Nibayii awọn onwoye atawọn ọmọ ẹgbẹ ṣi n reti igbesẹ ti awọn ọmọ igbimọ eleto idibo fun idibo naa labẹ alaga gomina ipinlẹ Jigawa yoo gbe lori eto naa.
To n tumọ si pe wọn ko tii le sọ boya alaga ọhun yoo wọgile eto naa gẹgẹ bi awọn oludije mẹfa naa ṣe beere fun ni tabi yoo tẹsiwaju lati kede ẹni to ba jaweolubori gẹgẹ bii oludije sipo gomina ninu ẹgbẹ wọn.
Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?
Ìdìbò láti yan olùdíje APC fún ipò gómìnà ṣì ń tẹ̀síwájú - Ìgbìmọ̀ APC

Igbimọ to n ṣe aayan ibo lati yan oludije fun ipo gomina ipinlẹ Ekiti ti kede pe ko si ounyẹ kan ko le yẹ eto naa.
Awọn mefa ninu awọn oludije mẹjọ to n dije ni wọn peju si olu ileeṣẹ ẹgbẹ oṣelu APC lati fi ẹhonu han lẹyin ti wahala kọkọ bẹ silẹ lowurọ Ọjọbọ ti wọn si kede pe ko si ohun to n jẹ idibo naa mọ atipe awọn ko nipin ninu rẹ mọ.
Wọn fi ẹsun kan gomina ipinlẹ Ekiti pe oludije kan to n ṣe agbodegba fun lo n da madaru silẹ ninu eto naa.
Wọn fẹsun kan oludije kan lara wọn pe o ti ragabo awọn ohun elo idibo naa ti o si ti n kọ ọ nibiamu oẹlu ohun to fẹ.
Atẹjade ti igbimọ naa fi sita ṣalaye pe aparo kan ko ga jukan lọ lori eto naa
Atẹjade naa ti akọwe igbimọ naa, Ọgbẹni Victor Ọlabimtan ṣalaye pe gbogbo awọn oludije lo pawọpọ yan awọn oṣiṣẹ eleto idibo ti wọn lo fun idibo naa.

Olùdíje gómìnà APC méje nínú mẹ́jọ fọnmú l'Ekiti lórí ìbò abẹ́nú

Wahala ati bilisi lo bẹ silẹ nibi igbaradi eto idibo lati yan oludije ti yoo gbe aṣia AapC ni ibo gomina ipinlẹ Ekiti to n bõ losu kẹfa.
Ni ojumọ ọjọbọ lawọn oluwode kan ti kọkọ ya bo olu ileeṣẹ ẹgbẹ iselu APC to wa lagbegbe Ajilosun nilu Ado Ekiti nibi ti wọn ti n fi ẹhonu han pe ọkan lara awọn oludije naa ti se ayederu.
"Loru moju ni wọn ti tẹ ibo mọju arumọjẹ ni wọn kan fẹ wa ṣe lowurọ yii"
- Pásítọ̀ mi bá àbúrò mi ṣe àṣemáṣe, gba mílíọ́nù àkọ́kọ́ tí mo pa bíi òṣèré tíátà, ó tún já ojú òpó ayélujára mi gbà - Toyo baby
- Ọwọ́ Sọ́jà tẹ 100 afurasí jàńdùkú tó fẹ́ da ìbò abẹ́nú PDP rú l‘Ekiti
- Ìyè èèyàn mélòó ní wọ́n dáná sun pẹlú Kábíyèsí Agodo?ọlọ́pàá tú àṣírí
- Bisi Kolawole, àyànfẹ Fayose ni olùdíje PDP fún ipò gómìnà l’Ekiti
- Ìgbẹ́jọ́ Baba Ijesha forí sánpọ́n, agbẹjọ́rò rẹ̀ kò yọjú sílé ẹjọ́
- Afenifere ń gbèrò láti dá ẹgbẹ́ òṣèlú sílẹ̀, àgbà Yoòbá kan ní àbùkù ni yóò gbẹ̀yìn rẹ̀
Bi iwode naa se n lọ pẹlu oniruuru iwe pelebe alakole lawọn janduku kan ya bo wọn pẹlu okuta ati ibọn.
Lakolako ni iro ibọn naa bẹrẹ si ni dun ti awon eeyan si fọnka. Gbogbo awon to ni ṣọbu sibẹ ni wọn bẹrẹ si nii ti ṣõọbu wọn.

Ifarahan awọn oludije kan si olu ileesẹ naa lo mu ki alaafia diẹ ko pada sagbegbe naa.
Lasiko ti a fi n ko iroyin yii jọ awọn oludije ti n ṣe ipade lati mọ o a abayo si laasigbo yii


Ijọba Ekiti ti ile ẹkọ pa nitori ibo abẹnu APC:
Wayi o, Ijọba ipinlẹ Ekiti ti kede oni Ọjọbọ gẹgẹ bi ọjọ isinmi lẹnu iṣẹ fun gbogbo awọn ile ẹkọ alakọbẹrẹ ati girama ni ipinlẹ naa.
Atẹjade kan ti oludari ileẹkọ nileeṣẹ eto ẹkọ nijọba ipinlẹ Ekiti, Ọgbẹni O.R. Ajayi fi sita rọ awọn adari ati olukọ ileẹkọ to jẹ tijọba ati aladani lati tẹle aṣẹ naa.
Bi o tilẹ jẹ pe wọn ko sọ idi ni pato ti wọn fi gbe awọn ileẹkọ alakọbẹrẹ ati girama ti pa, iwadii BBC News Yoruba fihan pe ko lee ṣai nii ṣe pẹlu eto idibo lati yan oludije fun ipo gomina labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu APC.
Eto idibo abẹnu naa ni yoo waye ni gbogbo wọọdu mẹtadinlọgọsan (177) kaakiri ijọba ibilẹ mẹrindinlogun n'ipinlẹ Ekiti.
Ìlànà gbogbo wa lá dìbò ni ẹgbẹ́ onígbálẹ̀ yóò lò láti yan olùdíje gómìnà
Ilana oju awo lawo fii gbọbẹ ti oloyinbo n pe ni "direct primaries" ni ẹgbẹ oṣelu APC fẹ lo fi yan oludije rẹ lọtẹ yii.
Ni Ọjọru ni ẹgbẹ oṣelu PDP seto idibo lati yan oludije tirẹ ninu eyi ti Ọtunba Bisi Olayinka ti kogoja pẹlu ibo asoju ọrinlelẹgbẹta o din mẹsan an (671).
Ero idibo sipo gomina ni ipinlẹ Ekiti yoo waye ni ọjọ kejidinlogun oṣu kẹfa ọdun 2022 gẹgẹ bi ajọ eleto idibo ni Naijiria, INEC ṣe gbe e jade.
Bi idibo abẹnu ẹgbẹ APC ba si se n lọ ni Ekiti, la maa mu wa fun yin.

















