Elephant kills Tourist in Uganda: Àlàyé rèé lórí bí erin ṣe tẹ arìnrìnàjò afẹ́ kan pa

Oríṣun àwòrán, AFP
Adura ti ọpọ eeyan ma n se ni pe ki Ọba oke mase jẹ ka rin arinfẹsẹsi, ka ma bọ sọwọ ohun ti yoo jẹ wa.
Amọ adura yii ko gba fun ọkunrin Arìnrìn-àjò kan ni ọgba àwọn ẹranko to wa ni orílẹ̀ èdè Uganda.
Idi ni pe se ni Erin tẹ paa nigba to bọ́lẹ̀ nínú ọkọ tó ń gbé rin ìrìn àjò.
- Kí ló pa akẹ́kọ̀ọ́ ọmọ Nàíjíríà tó kú lọ́jọ́ kejì tó dé ilé ẹ̀kọ́ ní Ukraine?
- Pásítọ̀ mi bá àbúrò mi ṣe àṣemáṣe, gba mílíọ́nù àkọ́kọ́ tí mo pa bíi òṣèré tíátà, ó tún já ojú òpó ayélujára mi gbà - Toyo baby
- Ọwọ́ Sọ́jà tẹ 100 afurasí jàńdùkú tó fẹ́ da ìbò abẹ́nú PDP rú l‘Ekiti
- Àlàyé rèé lórí ìròyìn tó ní Buhari ti kú, Jubril Sudan ló ń darí Nàíjíríà
- Timothy Adegoke yóò wọ ilẹ̀ sùn lọ́jọ́ Àbámẹ́ta, bí ìsìnkú rẹ̀ yóò ṣe lọ rèé
- Ìyè èèyàn mélòó ní wọ́n dáná sun pẹlú Kábíyèsí Agodo?ọlọ́pàá tú àṣírí
- Afenifere ń gbèrò láti dá ẹgbẹ́ òṣèlú sílẹ̀, àgbà Yoòbá kan ní àbùkù ni yóò gbẹ̀yìn rẹ̀
Bawo ni isẹlẹ naa se waye:
Olóògbé náà, tó jẹ́ ọmọ ilẹ̀ Saudi, ló ń gba ọgbà Murchison Falls lọ sí ìlú Arua kó tó sọ̀kalẹ̀ nínú ọkọ láti tọ̀.
Níbi tó ti ń ṣẹ̀yọ̀ọ́ yìí ni àwọn erin yà bò ó, tí kò sì rí bi sá wọnú ọkọ̀ nítorí ó ti rìn jìnà síbi tí ọkọ̀ wà.
Àwọn alámòjútó ọgbà náà fìdí ìṣẹ̀lẹ̀ tó wáyé lọ́jọ́ Ìṣẹ́gun náà múlẹ̀, tí wọ́n sì ní ìwádìí ń lọ lọ́wọ́.
Wọ́n fi kun pé àwọn ń gbìyànjú láti rí dájú pé irú rẹ̀ kò wáyé mọ́.
Irúfẹ́ ìkọlù báyìí látọwọ́ àwọn ẹranko ló ti máa ń wáyé ní àwọn ọgbà ẹranko ni Uganda.

















