Nollywood: Kìí ṣe nǹkan ìtìjú pé èmi ni mò ń gbọ́ bùkátà ẹbí mi - Nkechi Blessing

Oríṣun àwòrán, Nkechi
Gbájúgbajà òṣèré Nollywood Yoruba Nkechi Blessing Falegan pe kò sí ǹǹkan ìtìjú fún òun láti jẹ́ ẹni to n gbọ́ bùkátà àwọn ẹbi òhun.
Ojú òpó Insagram rẹ ló ti fi ìdí ọ̀rọ̀ yìo múlẹ̀ lásìkò tó n ṣe ìránti oṣù kan ti ìyá rẹ re ibi àgbà n re.
Gbajúgbajà òṣèré náà pàdánù ìyá rẹ lẹ́yín ọjọ́ díẹ̀ sí ayẹyẹ ọjọ́ ìbí rẹ̀, tí ó sì ṣe ẹ̀yẹ ìkẹyìn fún ìyá rẹ ni ọ̀eẹ̀ tó kọjá.
- Àwọn agbébọn ya wọ ọgbà ẹ̀wọ̀n ní Oyo, wọ́n tú àwọn ẹlẹ́wọ̀n sílẹ̀
- Sunday Igboho ní òun tí gbúró olóṣèlú kan tó fẹ́ fi orúkọ rẹ̀ gbokùn lọ́dọ̀ ààrẹ, òkò ọ̀rọ̀ tó fi ránṣẹ́ síi nìyí
- Gbẹgẹdẹ fẹ́ gbiná láàrín Oluwo àtàwọn ìgbìmọ̀ Ìmáàmù àti Àlfáà ilẹ̀ Yorùbá, wọ́n ní Oluwo ń kọjá àyè rẹ̀
- Ẹ fi ọkàn balẹ̀, a o ṣàfihàn gbogbo àbájáde ìwádìí ìgbìmọ̀ Endsars - Babajide Sanwo-Olu
- Àwàdà kẹrí-kẹrì ni ẹ̀sùn ìgbésùnmọ̀mí tí Malami fi kan Sunday Igboho - Ilana omo Oodua

Oríṣun àwòrán, Nkechi Blessing
Lẹ́yìn ayẹyẹ ọkú náà ni òṣèré ọhún lọ sí ilẹ Gẹ̀ẹ́sì láti lọ bá ọkọ rẹ David Adelegan tí kò sí nibi ayẹyẹ ìsìnku ìyá Nkechi Blessing.
Ó ṣàlàyé pé, ìyá òun àti ẹbi tí òin nílò láti gba bùkàta wọn ó fàá tí òun fi n ṣe iṣẹ àṣefẹ́ẹ̀kú, kìí ṣi ṣe ohun ìtìjú rárá.
Ní báyìí òṣeré náà ni òun ṣeetan láti padà sí ẹnu isẹ́ àti láti tẹ̀síwájú lẹ́nu iṣẹ́.
Nkechi Blessing dúpẹ́ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ènìyàn tó dúró tìí lásìkò ìsìnkú ìyá rẹ̀.














