Major General Farouk Yahaya: Ààrẹ Buhari tí yan olórí ikọ̀ ọmọogun Naijiria tuntun

Oríṣun àwòrán, Defence HQ
Aarẹ orilẹede Naijiria, Muhammadu Buhari ti yan Ọgagaun Major General Forouk Yahaya gẹgẹ bi Adari ikọ awọn ọmọogun ori ilẹ ni Naijiria.
Ninu atẹjade ti ẹka iroyin ileeṣẹ ọmọogun Naijiria fi lede ni iroyin naa ti han si awọn araalu.
Ọgagun Farouk ni oun dari ikọ awọn ọmọogun Naijiria to n koju ikọ Boko Haram ni ariwa orilẹede Naijiria, ti wọn pe ni HADIN KAI.
- Àwọn Ọ̀gágun tó ṣeéṣe kó gba ipò olórí àwọn ọmọogun lẹ́yìn ikú Attahiru nìyìí
- Ijamba ọkọ-ofurufu ologun pa 'yan mẹjọ
- Ariwo ẹkún sọ níbi ìsìnkú àwọn akọni tó bá ìjàmbá ọkọ̀ Bàálù lọ ní Abuja
- Ọkọ́ mi lá àlá pé bàálù já, kó tó kú nínú ìjàmbá bàálù lọ́jọ́ kẹta - opó olóògbé
- 'Ẹ jọ̀wọ́ ẹ bá wá fún àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò Taiwo Asaniyi níṣẹ́, òun ló ń bọ́ wọn kó tó kú nínú ìjàmbá bàálù'
- Ọdún 32 ni mo fi ṣiṣẹ́ oko mọ́ ìṣẹ́ tíṣà kí àwọn ọmọ mi le jẹ́ èèyàn, àmọ́ ikú mú Taiwo lọ - Baba Taiwo Asaniyi
- Àwọn ọmọ Naijiria n sọ òkò ọ̀rọ̀ sí Buhari àti Osinbajo pé wọn kò lọ sí ìsìnkú Ibrahim Attahiru
- Èpè elépè kò ní ràn ẹ́, aya Ajeyemi! Wo àwọn òṣèré tó ń fi àdúrà ré èpè ESABOD kúrò lóríi Toyin Abraham
Aarẹ Buhari yan adari ikọ tuntun fun awọn ọmọogun Naijiria naa lẹyin ijamba ọkọ ofurufu to mu ẹmi Ọgagun Ibrahim Attahiru lọ ati awọn ọmọogun mẹwaa miran.
Ileeṣẹ ikọ ọmọogun ofurufu naa ni awọn ṣi n ṣe iwadii ijamba ọkọ ofurufu to waye ni tosi papakọ ofurufu to wa ni ilu Kaduna.
Tani Ọgagun Farouk Yahaya ti wọn ṣẹṣẹ yan?
- Ọgagun Faruk Yahaya lo n dari ikọ ọmọogun to n gbogun ti Boko Haram lọwọlọwọ ni iwọ ariwa orilẹede Naijiria.
- Ipinlẹ Zamfara ni Faruk Yahaya tisẹ wa, to si di ipo gboogi mu ni ikọ ọmọogun Naijiria.
- Saaju o ti fi igba kan di ipo adari ikọ ọmọogun ilẹ Naijiria ri, iyẹn Commander of the Armed Forces.Ọgagun Faruk Yahaya










