Delegates in Nigeria: Ǹkan tí àwon omo Naijiria ń so nípa ''delegates'' tó ń dìbò fún egbé òsèlú ní yìí...

APC ati PDP

Oríṣun àwòrán, Others

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Ǹkan tí àwon omo Naijiria ń so nípa ''delegates'' tó ń dìbò fún egbé òsèlú ní yìí...

Lati ibẹrẹ ọsẹ yii ni awọn eniyan ti n sọrọ nipa awọn aṣoju ''delegates'' yii ati idi ti awọn ẹgbẹ oṣelu yii ṣe n fun wọn ni agbara lati dibo ṣoju awọn eniyan.

Lati ibẹrẹ ọsẹ yii ni awọn eniyan ti n sọrọ nipa awọn aṣoju ''delegates'' yii ati idi ti awọn ẹgbẹ oṣelu yii ṣe n fun wọn ni agbara lati dibo ṣoju awọn eniyan.

Awọn aṣoju wọn yii ni wọn n gba owo lọwọ awọn oludije, ti wọn si n dije fun awọn oloṣelu ti wọn ba fẹ.

Saaju idibo apapọ ti ọdun 2023, awọn aṣoju wọn yii ni apo wọn ti ku nitori awọn eniyan bẹrẹ si ni mọ wọn paapaa lori ẹrọ ayelujara.

Kini awọn eniyan n sọ lori ẹrọ ayelujara?

Ọkan lara awọn ọrọ to n ja ranyin lori ẹrọ ayelujara ti awọn eniyan n sọrọ nipa rẹ ni #delegates, paapaa loju opo ikansiraẹni Twitter.

Lara awọn ohun to n kọ awọn eniyan lominu ni bi awọn oludije ṣe n fun awọn aṣoju oludibo yii ni owo ni gbangba.

Àkọlé fídíò, Children Day 2022: Àwa Obìnrin kìí ṣe àpínmógún, àtẹ̀mẹ́rẹ̀; àwa ní iyọ̀ àti ìrèké ayé

Ero ọpọ eniyan ni wipe lilo ọna awọn aṣoju yii ko fun awọn eniyan ni anfaani lati dibo yan ẹni ti wọn fẹ ni ijọba tiwantiwa.

Ajafẹtọ obinrin ni Naijiria, Aisha Yesufu ti ni awọn aṣoju yii ko ba dibo yan ẹni ti awọn eniyan fẹ, ki wọn ma dibo fun ẹgbẹ naa ni igba ti akoko idibo gbogboogbo ba de.

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

Bakan naa ni Ajafẹtọ Rinu Oduala ni lilo awọn aṣoju lati dibo yan awọn oludije ni ẹgbẹ oṣelu ko ba ilana oṣelu tiwantiwa lọ.

O ni ohun ti awọn eniyan n tele ni owo ati ọla awọn oludije naa, nitori naa ẹni to ba ni owo ju ni yoo ni ibo to pọju lọ

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2

Farooq Kperogi to ma n gbohun si afẹfẹ nipa ọrọ Naijiria ni o ṣeni laanu bi awọn ọmọ Naijiria ti wọn pe ni aṣoju oludibo se n ta ibo wọn ni gbangba lai si ibẹru.

Àkọlé fídíò, Ayodeji Rotinwa ni ìròyìnn òfegè gbé àwòrán rẹ̀ síta pè dókítà tó ń pa àwọn Hausa mùsùlùmí

Kperogi ni eyi buru jai fun eto oṣelu ni orilẹede Naijiria.

O ni ohun ti yoo ṣẹlẹ ni ọdun 2023 ni ki awọn adari ra ibo lọwọ awọn aṣoju nitori naa eeru ni esi idibo naa yoo jasi ni apapọ.

Bakan naa ni iroyin gbe e pe awọn oludije kan gba owo wọn pada lọwọ awọn oludibo lẹyin ti wọn ko bori ninu idibo abẹle naa.

Àkọlé fídíò, Oba Adedokun Abolarin ti Oke Ila: Ó ya ọ̀pọ̀ tó súnmọ́ mi lẹ́nu bí mo ṣe ń kọ́

Amọ sẹnetọ Shehu Sani ni awọn oludibo meji lo dibo fun oun ti oun ko si fun wọn ni nkankan.

Skip X post, 3
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 3

Àkọlé fídíò, 'Ọ̀pọ̀ ìgbà l'èmí gan fẹ́ du àwọn ipò òṣèlú kan, bíì '2015, 2019' àmọ́ mo tẹ 'slow' torí bàbà mi, Akala náà ń jáde'