Óṣe! Onífàyàwọ́ epo bẹntiróòlù kan àti ìyàwó rẹ̀ jóná mọ́lé , wọ́n fi ọmọ osù mẹ́rin sílẹ̀ sáyé

Oríṣun àwòrán, Others
Ìṣẹ̀lẹ̀ láabi kan bẹ́ sílẹ̀ ní ìlú Jos, olú ìlú ìpínlẹ̀ Plateau bí ọkùnrin kan tó jẹ́ olówò epo bẹntiróòlù, Gideon Pam àti ìyàwó rẹ̀ jóná malé nínú ìjàmbá iná tó sọlè ní ilé ìgbé wọn.
Òkú Pam àti ìyàwó rẹ̀, Mercy ló jóná ráúráú níbi ìjàmbá iná tó bẹ̀rẹ̀ láti ilé ìdáná wọn tó sì gba gbogbo ilé kan.
Ìròyìn ní èpò bẹntiróòlù tí Pam gbé sílé fún títà gẹ́gẹ́ bí oníbàràǹdà bí ọ̀wọ́n gógó epo bẹntiróòlù ṣe ń bá ìlú fínra ló ṣe okùnfà iná náà.
- .Ìtàn Àrọ̀gìdìgbà jẹ́ kí ń rò pé bàbá mi yan Yemọ̀ja ní àlè - Ọmọ Fagunwa
- Mọ̀ sí i nípa Oba Yesufu Asanike, Olubadan tí kìí fi ọ̀rọ̀ sí abẹ́ ahọ́n sọ kódà níwájú sọ́jà
- Awẹ́ Gbólóhùn ni kókó tí à ń gbéyẹ̀wò lónìí lórí ètò Akomolede- Olùkọ Olajide
- Wo bí wọ́n ṣe sin Ọba Satani pẹ̀lú ọkọ̀ àti orin tó fẹ́ràn jù
- Àwọn Oba Yorùbá kan rèé tí wọ́n rọ̀ lóyè, tí Oba míràn jẹ lójú ayé wọn
- Iṣẹ́ Oníbúrẹ́dì ní mo kọ́, ìfẹ́ àṣà Yorùbá ló sún mi dé ìdí ẹ̀ṣà pípé tí mo fi là- Ajobiewe
- Ọba Lamidi Adeyẹmi, òṣìṣẹ́ adójútòfò àti Abẹ̀ṣẹ́kùbíòjò kó tó jọba
- Àwọn Olùkọ́ Akure pegedé lórí ètò Akomolede àti Aṣa lórí BBC Yorùbá
Báwo ni ìjàmbá iná náà ṣe wáyé?
Ìròyìn ní àwọn onílé epo kan ló pe Pam láti wá gbe epo bẹntiróòlù ti wọ́n ti bá a tà kalẹ̀, èyí ló mú Pam sáré lọ sí ilé rẹ̀ láti lọ gbé gálọ̀nù tí yóò ra epo náà sí.
Nígbà tó délé, tó ń gbìyànjú láti da bẹntiróòlù kúrò nínú àwọn gálọ̀nù tó ní epo bẹntiróòlù láti lọ fi ra èyí tí wọ́n pè é sí nínú ilé ìdáná wọn ni iná náà ṣẹ́yọ.
Iná yìí gbilẹ̀ tó sì gba gbogbo ilé kan débi pé Pam kò ríbi móríbọ́ nínú ìjàmbá náà.
- Ọlọ́pàá tó gbé oúnjẹ tẹ̀lé ènìyàn nínú fọ́nrán tó gba ìgboro yóò fojú winá òfin
- Ohun ìṣeré abánilòpọ̀ há sójú ara mi, mo kú tán - Obìnrin ológun kan
- Wo àwòrán bí Ukraine ṣe rí tẹ́lẹ̀ ṣáájú ìkọlù Russia àti bó ṣe rí báyìí
- Ìdí rèé tí mo ṣe fẹ́ jẹ ààrẹ Nàíjíríà - Tinubu
- Ẹ sọ́ra fún wíwá owó òjijì ẹ̀yin ọ̀dọ́, ìgbẹ̀yìn rẹ kìí dára- Alake Egba
- Ibá Lassa fojú hàn ní ìpínlẹ̀ Oyo, ó ti mú ẹ̀mí Dókítà méjì lọ
- Sé Nàìjíríà le fi Abba Kyari ráńṣẹ́ sí Amẹ́ríkà pẹ̀lú bó ṣe ń kojú ìgbẹ́jọ́ àjọ NDLEA? – Àlàyé rèé
Bawo ni Tokotaya se wa jọ jona mọ́le?
Ìyàwó Pam fẹ́ dóòlà ọkọ rẹ̀ ni òun náà fi há sínú ìjàmbá iná náà.
Bí iná yìí ṣe ń jó ní Mercy darí sílé láti ọjà ló ba tí èéfí ń ṣẹ́yọ láti ilé wọn.
Ní kété tó gbọ́ wí péw ọkọ òun ti ha sínú iná náà ní òun náà bá sáré wọlé láti lọ dóòlà ọkọ rẹ̀ nínú ìjàmbá iná yìí ṣùgbọ́n tó jẹ́ òkú òun náà ni wọ́n gbé jáde níbẹ̀.
Alábàgbé àwọn tọkọtaya náà, Shantel Alphonsus ṣàlàyé pé oníbàràǹdà epo bẹntiróòlù ni Pam ní oríta Zawan ní Jos.
Alphonsun fi kun pe ọmọ oṣù mẹ́rin ni àwọn tọkọtaya náà fi si ayé lọ.
Ó ní ìyá Pam ló gbé ọmọ náà ṣeré lọ ní òwúrọ̀ kí ìṣẹ̀lẹ̀ láabi náà tó wáyé.
Adarí ilé iṣẹ́ panápaná ìpínlẹ̀ Plateau, Caleb Polit fìdí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí múlẹ̀ àti pé gbogbo ilé náà ti jó tán kí àwọn tó le dé ibẹ̀.















