Obìnrin kan dèrò àtìmọ́lé fún ẹ̀sùn wíwẹ ọmọ rẹ̀ lómi gbígbóná nítorí kọ́kọ́rọ́

Omo naa

Oríṣun àwòrán, Others

Àjọ ẹ̀ṣọ́ ara ẹni làbò ìlú (NSCDC) ti fi obìnrin kan sí àhámọ́ fún ẹ̀sùn dída omi gbígbóná lé ọmọ rẹ̀, ọmọ ọdún mọ́kànlá ní Ìpínlẹ̀ Osun.

Nígbà tó ń fìdìí ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún múlẹ̀, ọ̀gá àgbà àjọ NSCDC ní ìlú Osogbo, Emmanuel Ocheja sọ wí pé àwọn ará àdúgbò obìnrin náà ló wá fi ọ̀rọ̀ ọ̀hún tó àwọn létí.

Kini ileeṣẹ agbofinro n sọ?

Ocheja ni ìwádìí ṣì ń lọ lọ́wọ́ láti fìdí ohun tó ṣẹlẹ̀ gan-an múlẹ̀, à ti pé ọmọ tí ìyá rẹ̀ da omi gbígbóná lé lórí ti wà ní ilé ìwòsàn fún ìtọ́jú.

Nígbà tí àwọn akọ̀ròyìn bèrè lọ́wọ́ obìnrin náà ohun tí ó ṣokùnfà tí ó fi da omi gbóná lé ọmọ rẹ̀ lára.\

O ní oun kò mọ̀ bí ọ̀rọ̀ náà ṣe jẹ́, à ti pé òun kò mọ̀ ọ́n mọ̀ da omi gbóná lè ọmọ òun lára.

Àkọlé fídíò, Tọktaya afọju ti Eledua tun fi ibeji ta lọrẹ

Nígbà tí ọmọ ń ṣàlàyé ohun tó ṣẹlẹ̀ láàrín òun àti ìyá òun, ó ní ìyá òun ń bá òun wí fún sísọ kọ́kọ́rọ́ kan nù ni.

Àjọ NSCDC tún ṣàfihàn ọkùnrin kan, ẹni ọdún mẹ́rìnlélógójì, Amos Danbaba Galadima fún wíwa kùsà lọ́nà àìtọ́ ni agbègbè Ita-Obi ni ìlú Ilesha, àti Abdulrahmon Ibrahim fún ẹ̀sùn pé ó jí ọkọ gbé ní Ìpínlẹ̀ Kano.