Ekiti state PDP Congress: Fayose, Olujimi, Oni ń forígbárí nítorí ìdìbò wọ́ọ̀dù tó wáyé lẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP l'Ekiti

Aworan Sẹnetọ Abiọdun Olujimi ati Oloye Ayọ Fayoṣe

Oríṣun àwòrán, Others

Ina edeaiyede n jo laarin awọn eekan oloṣelu lẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Ekiti paapaa laarin igun gomina tẹlẹ, Ayọ Fayose ati igbakeji rẹ nigbakan ri to tun jẹ sẹnetọ lọwọ bayii nileegbimọ aṣofin apapọ Naijiria.

Ko si ohun meji to n fa awuyewuye laarin wọn ju abajade eto idibo ati yan awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP ni wọọdu to waye nipinlẹ Ekiti lọjọ Satide, ọjọ karundinlogun oṣu kinni ọdun 2022.

Ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, Sẹnetọ Abiọdun Olujimi ṣalaye pe lara ọna ati mu iṣọkan igbọraẹniye ati alaafia pada sagbo ẹgbẹ naa nipinlẹ Ekiti lawọn fi wo eto naa.

O ni igbagbọ awọn ṣaaju eto naa ni pe gbogbo ẹgun iṣaaju to da wahala silẹ ni wọn yoo dana sun.

Amọsa, o ni ọrọ ko ri bẹẹ nigba ti awọn rii pe meji ninu awọn eeyan to wa nidi wahala naa lati ipilẹ wa ni wọn tun yan lati ṣe akoso idibo aṣoju naa.

Àkọlé fídíò, Sikiru Alabi

Sẹnatọ Abiọdun Olujimi fi ẹsun kan Oloye Ayọ Fayose pe oun gan ni eku ẹda to n da ina alaafia PDP ru paapa pẹlu ti idibo aṣoju wọọdu naa.

Sẹnetọ naa ṣalaye pe inu kọrọ ile kan ni awọn igun OPA to jẹ ti Fayoṣe ti kọ orukọ awọn aṣoju ti wọn fẹ laifi ti awọn igun ti 'Repositioning' to wa pẹlu Olujimi ṣe.

Ayọ Fayoṣe

Oríṣun àwòrán, others

Ki ni Fayose sọ?

Amọṣa ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, gomina tẹlẹ nipinlẹ Ekiti, Ayọdele Fayoṣe ṣalaye pe oun o ba ẹnikẹni ja.

O ni eeyan oun ni gbogbo wọn, oun ko si tii ṣe ohnunkohun to buru gẹgẹ bii aṣiwaju ẹgbẹ oṣelu naa.

Fayoṣe ṣalaye pe oun o mọ idi ti awọn oludije ti ọrọ kan ṣe n pariwo oun nigba ti wọn mọ pe oun kii ṣe Oludije.

Oṣoko, gẹgẹ bi orukọ inagijẹ ti ọpọ maa n pe e ṣalaye pe niwọn igba to jẹ wi pe nitori pe awọn oludije naa ri oun gẹgẹ bii eeyan pataki lagbo oṣelu ni wọn fi n da orukọ oun.

O ni gbogbo awọn ileeṣẹ agbofinro ni wọn ni akọsilẹ pe eto idibo ati yan awọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu PDP ni wọọdu waye nipinlẹ Ekiti, oun kọ lo si gba wọn siṣẹ.

Awọn agbaagba PDP nibi iwọde naa

Oríṣun àwòrán, Tvc

Fayose, Olujimi, Oni ń forígbárí nítorí ìdìbò wọ́ọ̀dù tó wáyé lẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP l'Ekiti

Lara awọn eekan oloṣelu ni ipinlẹ Ekiti to n gbaradi lati dije fun ipo gomina labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Ekiti, Biọdun Olujimi ati Ṣẹgun Oni fọn si igboro ilu Ado Ekiti lati ṣe iwọde takogomina ipinlẹ naa tẹlẹ, Ayọdele Fayose.

Àkọlé fídíò, Ọmọ ọdún mẹ́ta ni mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní lu ìlù, kí n tó di onílù Yinka Ayefele

Ẹsun ti wọn n fi kan Fayose ni pe o ti n dọwọ ru pẹlu ibo yiyan awọn adari ati aṣoju ẹgbẹ naa lẹsẹpupu wọọdu eyi to waye lọjọ Satide ọjọ karundinlogun, oṣu Kinni dun 2022.

Awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu PDP kan dara pọ wọ iwọde naa ti wọn si n ke sawọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa lati fofin de Fayoṣe lẹgbẹ oṣelu naa.

Wọn ni o n ṣe agbẹyinbẹbọjẹ fun gbogbo ilakaka awọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa nipa dida ṣe idibo yiyan awọn adari wọdu ni gbọngan adani rẹ kan lasiko to si jẹ pe ipade idibo ti ẹgbẹ fọwọ si gan n lọ kaakiri awọn wọọdu mẹtadinlọgọsan nipinlẹ naa.

Àkọlé fídíò, Fatimah Abode Lybia

Awọn oludije mejeeji naa wa ke sawọn adari ẹgbẹ oṣelu naa lati maṣẹ fọwọ kan iwe orukọ awọn adari wọọdu yoowu ti Ayọdele Fayose ba fi ranṣẹ si wọn nitori pe, ni ti awọn o, ipade idibo yiyan adari ẹgbẹ oṣelu PDP lawọn wọọdu nipinlẹ Ekiti ko waye.

Àkọlé fídíò, Eba

Ki ni olu ileeṣẹ ẹgbẹ oṣelu PDP sọ nipa idibo adari wọọdu nibẹ?

Awọn alaṣẹ apapọ ẹgbẹ oṣelu PDP ni awọn ti tẹwọ gba abajade ipade idibo yiyan awọn adari ati aṣoju ẹgbẹ naa lẹsẹpupu wọọdu lati ipinlẹ Ekiti.

Àkọlé fídíò, Ẹni bá láyà kó wá wọ̀ọ́! Ta ni Ìgè Àdùbí nílẹ̀ Oodua?

Ninu atẹjade kan ti wọn fi si oju opo ikanni Twitter ẹgbẹ oṣelu PDP awọn alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa ni awọn yoo wa ojutu si awọn aawọ to suyọ lasiko ipade idibo naa.

Àkọlé fídíò, Young Tolibian

Atẹjade ọhun ti alukoro ẹgbẹ oṣelu PDP lapapọ, Debọ Ologunagba fọwọ si ṣalaye pe bi wọn ṣe n tẹwọ gba esi idibo naa ni wọn tun tẹwọ gba awọn iwe ẹhonu latọdọ awọn mọ ẹgbẹ to ni ẹhonu kan kabi omiran.

Àkọlé fídíò, Arinrinoge ti eyin rẹ kán

O ni gbogbo rẹ ni wọn yoo yẹwo lati rii daju pe alaafia n jọba.