2023 presidency: Wo àwọn ọmọ Yorùbá mẹ́fà tí ẹnu ń kùn lórí ìbò ààrẹ ọdún 2023

Oríṣun àwòrán, Bola Tinubu
Bi ibo gbogbo ọdun 2023 ti n kan ilẹkun gbọngbọn ni awọn oludije fun ipo aarẹ ti n yọju lọkọọkan.
Ọpọ ọmọ Naijiria ni wọn ti n sọ nipa awọn to fẹ dupo aarẹ lọdun 2023 ti Aarẹ Muhammadu Buhari yoo gbe ijọba silẹ.
Pataki julọ ọpọ lo gbagbọ lẹkun iwọ oorun gusu Naijiria pe ẹya Yoruba ni ipo aarẹ kan lọdun 2023.
- Ki gan an ló mú kí awuyewuye pọ̀ lórí ìkéde èròngbà Tinubu láti du ipò ààrẹ Nàìjíríà?
- Wo ọmọ Nàìjíríà mẹ́fà tí ayélujára sọ di ìlúmọ̀ọ́ká
- Ẹgbẹ́ òṣèlú APC ti pín l'Osun, báyìí ni ọ̀rọ̀ ṣe di gbas gbos láàrin Aregbesola àti Oyetola
- Láìṣẹ̀, láìrò, Arákùnrin ẹni ọdún 43 fi ipá ba ìyá arúgbó ẹni ọdún 80 lo pọ
- Ìdìbò 2023: Àwọn ìpèníjà tí Bola Tinubu yóò kojú nínú ìrìnàjò rẹ̀ nìyí
Aṣiwaju Bola Tinubu, Dele Momodu ati Doyin Okupe wa lara awọn ọmọ Yoruba to ti fi erongba wọn han lati dupo aarẹ lọdun to n bọ.
Wọnyii ni awọn ọmọ Yoruba mẹfa ti ẹnu n kun lori ibo aarẹ ọdun 2023.
Bola Tinubu
Laipẹ yii Asiwaju Bola Tinubu kede erongba rẹ lati du ipo aarẹ orilẹede Naijiria.
Tinubu to jẹ eekan ninu ẹgbẹ oṣelu APC kan si aarẹ Muhammadu Buhari lọjọ Aje to kọja niluu Abuja lori erongba rẹ.
- Ọta ìbọn bá Pásítọ̀ tó ń gbàdúrà lórí òkè, ikú dé lójijì
- Tinubu hùwà ọdàlẹ̀, Ọlọ́run kó sì ní gbà fún un lórí èròngbà rẹ̀ - Ohanaeze Ndigbo
- Wo ìlú tí wọ́n ti ń gbé òkú ọba wọn pọ̀n lórí ẹṣin lọ fún ìsìnkú nínú igbó
- Àlàyé rèé lórí bí àwọn agbébọn ṣe pa ṣọ́jà méjì, ọlọ́pàá àtọ̀pọ̀ olùgbé ìletò kan ní Kebbi
- Wo ọmọ Nàìjíríà mẹ́fà tí ayélujára sọ di ìlúmọ̀ọ́ká
Lẹyin naa lo sọ fun awọn oniroyin pe oun ti fi to aarẹ leti pe oun fẹ dupo lọdun 2023.
Awuyewuye lo tẹle ikede Tinubu yii, oriṣiiriṣii nakn lawọn eeyan n sọ lori erongba Tinubu lati dije fun ipo aarẹ Naijiria.
Eekan ẹgbẹ oṣelu PDP, Oloye Bode George ni tẹ sọ pe awada kẹrikẹri ni ikede Tinubu to ni oun fẹ dupo aarẹ Naijiria.
Yemi Osinbajo
Igbakeji aarẹ Naijiria, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo jẹ ọkan lara awọn ọmọ ilẹ Yoruba ti ẹnu n kun fun ibo aarẹ ọdun 2023.
Bo tilẹ jẹ pe Osinbajo gan an fun ra rẹ ko tii kede pe oun maa dije fun ipo aarẹ lọdun 2023, oniruuru ẹgbẹ ni wọn ti bẹrẹ ipolongo fun igbakeji aarẹ.
Koda, olori orilẹede Naijiria tẹlẹ ri, ajagun fẹyinti Ibrahim Babangida gan buwọlu Osinbajo laipẹ yii gẹgẹ bi ẹni to le tukọ orilẹede Naijiria.
Awọn ẹgbẹ kan tiẹ sọ fun un pe ko si iru adehun ti o le ṣe pẹlu ẹnikan to le ni ki o maa dije fun ipo aarẹ.
Kayode Fayemi
Gomina ipinlẹ Ekiti, Kayode Fayemi naa wa lara awọn ọmọ ilẹ Yoruba ti ẹnu n kun lori ibo aarẹ ọdun 2023.
Fayemi gan an fun ra rẹ ko tii sọ fawọn ọmọ Naijiria pe oun yoo dupo aarẹ lọdun 2023.
Amọ, ọpọ lo gbagbọ wi pe gomina ipinlẹ Ekiti naa yoo kopa ninu ibo aarẹ ọdun 2023.
Doyin Okupe
Agbẹnusọ aarẹ ana, Goodluck Jonathan, Doyin Okupe naa ti kede bi Asiwaju Bola Tinubu pe oun ṣetan lati dupo aarẹ lọdun 2023.
Okupe ni labẹ asia ẹgbẹ oṣelu PDP ni oun yoo gbegba ibo aarẹ lọdun 2023.
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ èèyàn mẹ́rin tó ń jẹ́ ẹran ara èèyàn tí wọ́n tún ń tà ẹ̀yà ara èèyàn
- Bí EFCC ṣe mú ayédèrú ọ̀gágun sọ́jà Bolarinwa tó tún ní ẹ̀sùn jìbìtì owó N270m
- Ọkùnrin tó gbìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ìya rẹ̀ láti fi àbúrò rẹ̀ ṣẹ́ṣó kó sí gbaga Ọlọ́pàá
- O.Y.O ni Tinubu wa o, a kò ní ṣ'àtìlẹ̀yìn fún un ní 2023 àyàfi ... - Afenifere, Ilana Omo Oodua
- Àjọ NDLEA tanná wòdí Cubana
Okupe ni oun yoo ṣe ijọba ti yoo mu ọrọ awọn mẹkunnu lọkunkundun.
Bakan naa ni Okupe ṣeleri lati wa ojutu si ina ọba to n ṣe mọna mọna ti awọn ọmọ Naijiria ba le dibo fun oun.
Babatunde Fashola
Fun igba pipẹ ni ọpọ Naijiria ti n sọ pe o ṣeeṣe ki gomina ipinlẹ Eko tẹlẹ, Babatunde Fashola dije fun ipo aarẹ ọdun 2023.
Awọn ololufẹ Fashola gbagbọ pe oun lo gbangba sun lọyẹ lati tukọ orilẹede Naijiria pẹlu iriri iṣejọba ti o ti ni.
- Okòòwò márùn ún tí o lè bẹ̀rẹ̀ nínú ilé rẹ̀
- Ṣé ẹ ti gbọ́ nípa òògùn ìbílẹ̀ Coronavirus tí Ooni filọ́lẹ̀? Ó ní ẹgbẹẹgbẹ̀rún èèyàn tó ní Covid-19 ló ti gbádùn
- Ṣé o mọ̀ pé o leè kó Covid pẹ̀lú ọmọ ìka ẹ̀sẹ̀ rẹ̀ láì mọ̀?
- Bí Otunba Adebayo Alao Akala ṣe kú rèé, àti ibi tó dákẹ́ sí gangan - Amúgbálẹ́gbẹ́ Alao Akala
- A tí ṣé tań láti díje fuń ipò ààre ní ọdún 2023
- Wo àwọn èèkàn mẹ́rin tí Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ pàdánù láàárín oṣù kan
Ọpọ sọ pe Fashola gbiyanju nigba to fi jẹ gomina ipinlẹ Eko eyi to tumọ si pe yoo gbarada to le di aarẹ orilẹede Naijiria.
Koda, ọpọ eeyan ni wọn tun ti n lu u lọgọ ẹnu lori iṣẹ to n ṣe gẹi bi minisita akanṣe iṣẹ ati ilegbee.
Dele Momodu
Gbajúgbajà akọròyìn tó ti fi èròńgbà rẹ̀ láti díje dupò Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà lọ́dún 2023, Dele Momodu ti ní láti ọdún 2018 ni ẹnìkan ti fi àtẹ̀jíṣẹ́ ráńṣẹ́ sí òun wí pé òun yóò di Ààrẹ orílẹ̀ èdè yìí.Pásítọ̀ ti ríran sí mi pé mà á jẹ Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti ọdún 2018- Dele Momodu
Ó ní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun kò ká sí nígbà náà, àsìkò ti tó báyìí kí àlá onítọ̀hún wá sí ìmúṣẹ.
Dele Momodu ni ọmọ Yoruba to jẹ ẹni kẹfa ti a n sọrọ le lori lonii.






















