Dele Momodu: Mo ni gbogbo àmúyẹ láti tukọ̀ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní 2023

Dele momodu

Oríṣun àwòrán, @Dele Momodu

Àkọlé àwòrán, Dele Momodu setan lati di aarẹ Naijiria

Gbajúgbajà akọròyìn tó ti fi èròńgbà rẹ̀ láti díje dupò Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà lọ́dún 2023, Dele Momodu ti ní láti ọdún 2018 ni ẹnìkan ti fi àtẹ̀jíṣẹ́ ráńṣẹ́ sí òun wí pé òun yóò di Ààrẹ orílẹ̀ èdè yìí.

Ó ní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun kò ká sí nígbà náà, àsìkò ti tó báyìí kí àlá onítọ̀hún wá sí ìmúṣẹ.

Dele Momodu sọ èyí ní orí ẹ̀rọ ayélujára Facebook ní òwúrọ̀ yìí nígbà tó ń bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀.

Ó ní òun ní gbogbo ohun tó yẹ láti lè fi tu kọ̀ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà à ti pé òun Ọlọ́hun mọ̀ ọ́ mọ̀ pa òun mọ́ di àsìkò yìí.

Dele Momodu

Oríṣun àwòrán, @Dele Momodu

Àkọlé àwòrán, Dele Momodu

"Ẹni tí Nàìjíríà nílò lásìkò yìí ni ẹni tuntun tí kò ní nǹkan ṣe pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìbàjẹ́ àtẹ̀yìn wá".

"Mo ti ṣet'sn láti lo gbogbo ẹ̀bùn tí Ọlọ́hun fún mi láti fi sin Nàìjíríà".

Àkọlé fídíò, Fatimah Abode Lybia

Bákan náà ló fi kun un pé òun tí ń kó ipa ribiribi fún àwọn ènìyàn káàkiri orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nípa ṣíṣe àgbékalẹ̀ ìkúnpá owó.

Ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn ló ti ṣe ìforúkọsílẹ̀ fún ètò ìkúnpá owó náà lórí áàpù tì àwọn ṣàgbékalẹ̀ látọwọ́ obìnrin ará ilẹ̀ Ghana kan.

Dele Momodu

Oríṣun àwòrán, @Dele Momodu

Ó tẹ̀síwájú pé gbogbo ìpínlẹ̀ mẹ́rẹ̀rìndínlógójì orílẹ̀ èdè yìí ni àwọn ènìyàn ti ṣe ìforúkọsílẹ̀ tí àwọn sì ti ń ṣe ohun tí ipá àwọn ká fún àwọn tó nílò ìrànlọ́wọ́.