Nasarawa Rape: Ọwó ọlọ́pàá Nasarawa tẹ arákùnrin ẹni ọdún 43 tó fipá bá ìyá arúgbó lo pọ

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Láìṣẹ̀, láìrò, Arákùnrin ẹni ọdún 43 fi'pa ba ìyá arúgbó ẹni ọdún 80 lo pọ
Ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Nasarawa ti mu arakunrin ẹni ọdun mẹtalelogoji kan lori ẹsun pe o fipa ba iya arugbo kan lajọsepọ.
Eni ọgọrin ọdun ni iya arugbo yi.
- Gómìnà Wike dá rúgúdù sílẹ̀ láàárín ọlọ́pàá, Sífú dìfẹǹsì lórí ẹsùn fàyàwọ́ epo rọ̀bì
- Àwàdà ni pé Tinubu fẹ́ du ipò aàrẹ ní 2023- Bode George
- Gani Adams ṣàlàyé bí ìjọba àpapọ̀ ṣe ń dènà ìtúsílẹ̀ Sunday Igboho ní àhámọ́
- Ikú Esther Anguju ní ìpínlẹ̀ Nasarawa dá inú fu, àyà fo kalẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n fẹ̀sùn ìpànìyàn kan ọkọ rẹ̀
- Mọ̀ síi nípa àǹfàní tí lílo Àlùbọ́sà Aáyù lè fún ìlera ìwọ àti ẹbí rẹ
Atẹjade lati ọdọ alukoro ọlọpaa Ramhan Nansel lọjọ Aiku ni Lafia olu ilu Nasarawa lo fidi ọrọ yi mulẹ.
Gẹgẹ bo ti se wi, lọjọ Kẹrinla, osu kini ni wọn mu ẹjọ yi wa si agọ ọlọpaa Garaku.
Dan'asabe Eddo, to jẹ ọmọ bibi Kaduna ni afurasi taa n wi yi to si n gbe labule Garaku nijọba ibilẹ Lokongo.
"Wọn fẹsun kan an pe o fipa wọ ile arugbo ẹni ọdun ọgọrin to n da gbe ile yi to si fipa ba lajọsepọ''
Atẹjade naa tẹsiwaju pe "Kete ti a gbọ nipa isẹlẹ yi lawọn ọlọpaa agọ to wa ni Garaku gberasọ ti wọn si mu afurasi yi''
Alukoro ọlọpaa naa ni Kọmisọnna ọlọpaa Adesina Soyemi, ti pasẹ pe ki ẹka ọtẹlẹmuyẹ to wa ni Lafia bẹrẹ iwadii lori ọrọ naa.















