Ọwọ́ sìkún àjọ ọlọ́pàá orílẹ̀-èdè Náíjíríà tí ba àwọn ọlọ́pàá márùn ùn tó halẹ̀ mọ̀ arìnrìnàjò

Oríṣun àwòrán, Facebook/ngpolice
Njẹ ẹ ranti fọnran fidio kan to gba ori ayelujara kan nibi ti ọlọpaa kan ti n fi ibọn halẹ mọ obinrin kan loju ọna marosẹ ?
Awọn ọga rẹ ti gbe igbesẹ lori ọrọ naa lẹyin ti ariwo araalu gbode kan.
Ohun taa gbọ ni pe ileeṣẹ ọlọpaa ti kede pe awọn ti mu awọn ọlọpaa to halẹ mọ awọn arinrinajo kan loju ọna marosẹ Benin si Eko.
- A ó kó Ọlọ́pàá àti Sọ́jà síta lásìkò ìdìbò lòdí sí àwọn oní jàǹdùkú, ẹ ṣáà fọkàn tán mi - Buhari
- Ìyàwó Ẹlẹ́ṣìn ìlú Wukari yarí pé láyé òun ò lè gbà kí ọkọ́ òun wọ igbó mọ́ fún ìsìnkú Ọba
- Èèmọ̀! Ọmọ kíláàsì àgbà fi bíléèdì gé gògòńgò ọmọ kíláàsì wẹ́wẹ́, àlàyé rèé
- A ti fi kún owó ìtanràn fún ẹni tó ba da ẹran jẹ̀ nígboro Benue- Gómìnà Samuel Ortom
- Wo bí ọlọ́pàá ṣe rí òkú ọmọ ọdún márùn-ún tí wọ́n ní olùkọ́ rẹ̀ jígbé
Ninu fọnran fidio ti a ti ri aṣemase wọn,nise ni ọkan ninu awọn ọlọpaa yi fọ obinrin kan leti to si tun yinbọn mọlẹ lẹẹmeeji.
Atẹjade ti ileeṣẹ ọlọpaa fi sita loju opo wọn ni Facebook sọ pe sajẹnti Jude Ogudu ati awọn mẹrin mii wa ni ahamọ ẹka ọtẹlẹmuyẹ.
Bẹẹ ni wọn sọ pe awọn ti n se iwadii ọrọ naa nipasẹ ẹka wọn ti wn pe ni X-squad.
Ki la mọ nipa fọnran fidio aṣemaṣe awọn ọlọpaa yi
Ileeṣẹ ọlọpaa ninu atẹjade wọn sọ pe laarin ọjọ kẹtala si ọjọ Kẹẹdogun ni iṣẹlẹ yi waye lopopona marosẹ Benin si Eko.
Ninu fidio yi to wa kaakiri loju opo ayelujara, a ko le sọ nkan to fa ija ṣugbọn kedere la ri ti ọlọpaa kan,iyẹn Jude Ogudu n fi ibinu sọrọ.
Ko fi mọ ni ọrọ sisọ nikan, niṣe lo fọ obinrin kan leti to si loun yoo yinbọn pa.
- Oníbárà tí a bá mú lẹ́sẹ̀ títì yóò sùn ẹ̀wọ̀n- ìjọba Ìpínlẹ̀ Kwara
- Èèyàn 17 kú, 60 farapa níbí ìbúgbàmù kan tó wáyé ní ìlú Bogoso
- Ọkùnrin kan ná N20m tó ṣèèsi wọ inú àkáùǹtì rẹ̀, ó forí kó ẹjọ́
- Mínísítà fí ìkìlọ síta lẹyìn tí òjò àrọ̀rọ̀dá àti àrá sán pa èèyàn 82
- Àwọn nǹkan mẹ́fà tó so Ààrẹ Muhammadu Buhari pọ̀ mọ́ Ìpínlẹ̀ Kaduna
- Ìwádìí òótọ́: Ṣé igi àti pákó ni wọ́n tò sínú ìrẹsì gogoro tí Ààrẹ Buhari ṣe ìfilọlẹ̀ l'Abuja?
O yin ibọn rẹ mọlẹ ninu fidio yi ti awọn ọlọpaa rẹ to ku si n fa a wi pe ko ṣe suuru.
A ko ri oju arabinrin naa tabi ti awọn arrinrinajo to ku ṣugbọn o yẹ ki iwadii awọn ọlọpaa tan imọlẹ si iru ọrọ yi
Ọlọpaa ko ṣẹṣẹ maa halẹ mọ ara ilu
Lorileede Naijiria iṣesi awọn ọlọpaa si araalu jẹ eleyi to n kan ọpọ lominu.
Lọpọ igba ipa ati agidi ni wọn a maa fi ba araalu lopọ eleyi ti a si maa mu ikọlu wa.
Ọrọ yi lo mu ki ọpọ ọdọ ṣe iwọde taa mọ si #ENDSARS ni itako idunkoko mọ awọn araalu lati ọwọ ọlọpaa.
Toun ti bi awọn alaṣẹ ti ṣe n sọ pe awọn n kọ awọn ọlọpaa yi lẹkọ biba araalu sepọ to, awọn ti kii huwa bi ọmọluabi ṣi pọ ninu wọn.
Loju awọn opopona marose, ko jẹ tuntun ki eeyan ri awọn ọlọpaa ki wọn gbegi dina pe awọn n ṣe ayẹwo iwe ọkọ.
Lọpọ igba owo ni wọn a maa gba lọwọ awọn arinrinajo tabi dirẹba ọkọ ni tipa.
Igba tawọn awakọ tabi ero ba yari mọ wọn lọwọ lo maa n ṣe okunfa iru iṣẹlẹ taa ri ninu fọnran fidio yi.

















