Yoruba Nation agitation: Ilana Omo Oodua kò lọ́wọ́ sí ẹjọ́ ìbò 'Refrendum' kankan, àwọn tó ń ṣe é ń jíṣẹ́ ara wọn ni

Oríṣun àwòrán, other
Iroyin kan jade ni Ọjọbọ pe awọn ọmọ ẹgbẹ to n ja fun idasilẹ orilẹede Yoruba ti dara pọ mọ ẹjọ ti ẹgbẹ Coalition of Northern Groups , CNG fun ijọba lati fun ẹgbẹ Biafra to n ja fun idasilẹ orilẹede Igbo lanfani lati ṣeto ibo bẹẹni tabi bẹẹkọ lori idasilẹ orilẹede Igbo.
Amọṣa ẹgbẹ Ilana Ọmọ oodua to jẹ olori agbarijọpọ gbogbo ẹgbẹ to n ja fun idasilẹ ilẹ Yoruba ṣalaye pe awọn ko mọ nipa rẹ o.
Ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ, agbẹnusọ fun ẹgbẹ Ilana Ọmọ Oodua ṣalaye pe iroyin kayeefi lọrọ naa jẹ fun awọn nitori pe awọn ko figbakankan darapọ mọ ẹnikẹni lati pe ẹjọ tabi ṣe ẹjọ nipa ibo bẹẹni tabi bẹẹni kankan.
- Wo bí ọlọ́pàá ṣe rí òkú ọmọ ọdún márùn-ún tí wọ́n ní olùkọ́ rẹ̀ jígbé
- Oníbárà tí a bá mú lẹ́sẹ̀ títì yóò sùn ẹ̀wọ̀n- ìjọba Ìpínlẹ̀ Kwara
- Èèyàn 17 kú, 60 farapa níbí ìbúgbàmù kan tó wáyé ní ìlú Bogoso
- Níbo ni ìbọn 178, 549 wọlẹ̀ sí níléeṣẹ́ ọlọ́pàá Nàìjíríà?
- Wo bí ọlọ́pàá ṣe rí òkú ọmọ ọdún márùn-ún tí wọ́n ní olùkọ́ rẹ̀ jígbé
Kini èrò Ilana Omo Oodua lori agbẹjọrọ naa?
Ọgbẹni Maxwell ṣalaye pe ohun kan ṣoṣo to n ja lọkan gbogbo ọmọ Naijiria ni lati da eto idibo to n bọ lna ni ipinlẹ Ekiti ati Ọṣun duro lọna to tọna labẹ ofin.
O ni awọn igbesẹ naa yoo bẹrẹ si nii fi ara han fun araye ri laarin ọsẹ diẹ si asiko yii.
Ni Ọjọbọ ni amofin kan ti orukọ rẹ n jẹ Timilehin Odunwo farahan nibi igbẹjọ ẹjọ kan ti ẹgbẹ Coalition of Northern Groups , CNG pe ijọba apapọ pe ko ṣeto idibo bẹẹni tabi bẹẹkọ fun awọn ajijagbara Biafra lati m boya awọn eeyan eya wọn fẹ lati lọ nitootọ.
Amofin Odunwo to pe ara rẹ ni agbẹnusọ fun awọn to n pe fun idasilẹ orilẹede Yoruba, iyẹn Yoruba Nation ṣalaye pe idi ti oun fi n darapọ m igbẹjọ naa ni pe kii ṣe ilẹ Igbo nikan lo n ja fun ominra, ilẹ Yoruba pẹlu nifẹsii pẹlu.
- Èrò àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lórí ọ̀rọ̀ Gbajabiamila pé: Kò yẹ kí ẹni tí kò kà ju WAEC bíi Buhari jẹ Ààrẹ Naijiria mọ́
- Senato Olujinmi ní Fayoṣe ló ń dá PDP Ekiti rú, Fayose ni ọmọlẹ́yìn òun ni gbogbo àwọn tó ń fapájánú
- Èèmọ̀! Ọmọ kíláàsì àgbà fi bíléèdì gé gògòńgò ọmọ kíláàsì wẹ́wẹ́, àlàyé rèé
- Ọlópàá Benin márùn ùn tó halẹ̀ mọ̀ arìnrìnàjò nínú fónrán fídíò tí wà ní gbaga
- A ti fi kún owó ìtanràn fún ẹni tó ba da ẹran jẹ̀ nígboro Benue- Gómìnà Samuel Ortom














