UK Recession: Ètò ọ̀rọ̀ ajé ilẹ́ Gẹ̀ẹ́sì ti dẹnukọlẹ̀ fún ìgbà akọ́kọ́ láti ọdún 2009: wo bí ipa tí yóò ní lórí rẹ̀

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Fún ìgbà àkọ́kọ́ ní ǹkan bi ọdún mọ́kànlá sẹ́yìn orílẹ̀-èdè United Kingdom ti kédé pé ètò ọ̀rọ̀ ajé rẹ̀ ti dẹnukọlẹ̀.
Èyí sì túmọ̀ sí onírúurú ǹkan to lágbára fun ọ̀pọ̀ èniyàn nílé àti nílẹ̀ òkèèrè.
Ètò ọ̀rọ̀ ajé náà ti ti dẹnukọlẹ̀ láti ìdá ogún o lé díẹ̀ yàtọ̀ sí bí ó ṣe wà ni oṣù mẹ́ta àkọ́kọ́ nínú ọdún yìí.
- Ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ ń gbáradì láti gbéná wojú MTN, lórí bó ṣe ń ṣe àwọn òṣiṣẹ́ rẹ̀ ní Naijiria
- Àwọ̀ ojú pọ̀ bíi àwọ̀ òṣùmàrè, àmọ́ ojú búlúù Risikat kò nílò àtúnṣe- Dókítà
- Ìdí rèé tí a ṣe fẹ́ sin Majek Fashek sílẹ̀ Amerika- Randy Fashek
- Àwọn ǹkan tí ó yẹ kí o mọ̀ nípa 'Sharia Law' ní Nàìjíríà
- ‘Àwọn òlóṣèlú kò ní ìwà ọmọlúwàbí ló jẹ́ kí wọ́n má a lọ láti ẹgbẹ́ òṣèlú kan lọ sí òmìràn’
Owó ti àwọn ẹbi máa ń lò láti ràn ǹka sínú ilé kò tó mọ́, nígbà tí ilé ìtajà àti àwọn ilé iṣẹ́ to ń ṣe ǹkan èlò gbogbo kò fi bẹẹ ṣe ọ̀ps mọ́ nígbà ti ọ̀ps sì n gbé ilé iṣẹ́ wọ́n tà.
Ilé iṣẹ́ tó ń mójú to iye ènìyàn to wà nínú ìlú sàlàyé pé àwọn ilé-ìwé, ilé ìtajà, àti gbogbo ilé iṣk tó ti wà ní títì pa lásìkò Covid-19 náà ba ńkan jẹ́.
Èyí ló ti ilẹ̀ gẹ̀ẹ́sì sí ipò ti wan wà yìí ńitori kò fi kátàkára fún oṣù mẹ́fa láti ọdún 2009.

- À kò gba owó kankan lọ́wọ́ àwọn ẹgbẹ́ agbésùmọ̀mí ISWAP- MURIC
- Ẹlẹ́wọ̀n 44 kú sọ́gbà ẹ̀wọ̀n nítorí ooru tó mú púpọ̀
- Àwọn ǹkan tí ó yẹ kí o mọ̀ nípa 'Sharia Law' ní Nàìjíríà
- Joe Biden kéde Kamala Harris, obìnrin aláwọ̀ dúdú gẹ́gẹ́ bí igbákejì rẹ̀ nínú ìdíje sípò Ààrẹ Amẹrika
- Àmọ̀tẹ́kùn gbéra! Kò séwu nínú ìdìbò tó ń bọ̀ l'Ondo àfi gìrì àparò- Akeredolu
Ọ̀nà wo ni ìdẹnukọlẹ̀ ètò ọ̀rọ̀ ajé UK yìí yóò gbà láti kan ìwọ náà
Iṣẹ́/Owó
Ọ̀pọ̀ ènìyàn le pàdánù iṣẹ́ wọ́n, tàbi kí wan tni kò ní sí ìgbéga tàbi afówókún owó oṣù wọ́n kò ni wayé.
Ó tún ṣe é ṣe kí (Kódà àdínkù tún lè báa).
Fún àwọn ẹ̀yà aláwọ̀ dúdú tó ni ẹbi ni ilẹ̀ òkèèrè, èyí le jẹ́ ìpalára fún wọ́n nítorí, bi iná bá ń jóni, tó ń jó ọmọ ẹni... nítorí náà an yóò kọ́kọ́ gbọ́ ti ará ìlú kí wọ́n tó r'aàyé ti àwọn alejò.
Etò Ẹkọ / Awọn to ti kàwé tán
Àwọn ọmọ ilẹ̀ adúláwọ ti wọ́n fẹ̀ lọ sí ilẹ̀ òkèrè láti kàwé, kò ni sí owó ìrànwọ́ tàbi ètò ẹkọ ọfẹ́ nílùú òkèrè bi ti tẹ́lẹ̀ mọ́
Owó ilé-ìwé le wọ́n síi
Nítolrí ìdí èyí, ọ̀ps àwọn tó ti kàwé gboyè le ri pé yóò nira fún wọ́n ki wọ́n tó rí iṣẹ́ àkọkọ́ wọ́n.
Fún àwọn to sì fẹ wọ́ ilé Ẹ̀kọ́ gíga, ìdẹnukọlẹ ọ̀rọ̀ ajé yìí le jẹ́ ki wọ́n sún ìwọlé síwájú, nítori kò si owó ti wọ́n yóò fi ṣètò náà.

Oríṣun àwòrán, Nigeria Immigration Service
Fisà
Kò sí ẹni tó yé, iye ti owó ìwé ìrìnnà yóò jẹ́ yálà kí o wọ́n síi tàbi kó tún wálẹ̀. Ó sì tún ṣe é ṣe kí o nira láti ri ìwé ìrìnà lọ si ilẹ Gẹ̀ẹ́sì.
Jíjogún ìṣẹ́
Àwọn onímọ̀ ti sàlàyé pé, iṣẹ́ àti òṣì ti ìdẹnukọlẹ̀ ètò ọ̀rọ̀ ajé yìí yóò dá fún ẹbi míràn, ìran wọ́n kò ni lè san tán.
Ìdí ni pé, nígbà míràn, ó máa n nira láti bori àsìkò yìí tí ìṣk náà yóò tún ran àwọn ọmọ.
Ohun ìní
Àwọn ǹkan ìní ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì yóò wálẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn ló nílò owó, èyí yóò si jẹ́ ànfàni fún àwọn to ṣe idókodòwò ilẹ̀ okeèrè, to fi mọ́ àwọn to wá láti ilẹ̀ Afíríkà.
Àwọ onímọ̀ fi kún un pé, àwọn tó bá ni ié tàbi ill lé maa tàa. nítorí náà bákan méjì lọ́rọ̀ ọ̀hún.

Ọ̀rọ̀ ajẹe tó dẹnukọlẹ̀ lọ́dún 2009 kíló ṣẹlẹ̀ nigba naa?
Ìjàmbá tó ń bá ètò ọ̀rọ̀ aje to dẹnukọlẹ̀ rìn kò rí bákan náà fún gbogbo ènìyàn.
Èyí túmọ̀ sí pé, bí yóò ṣe kan olúkúlùkù kìí ṣe bákan náà, ó ṣe é ṣe kí ẹlòmíràn má tilẹ̀ mọ̀ ọ́ lára rárá.
Bí àpẹ̀rẹ ni ọdún 2009, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì tí wọ́n ni ilé ara wọ́n, ti wọ́n si tún ni iṣẹ́ lọ́wọ́ pada gbádùn nígbà ti ǹkan pada bọ̀ sípò.
Bákan náà ni ni àwọn tó ń sanwó èlé lórí ilé, ìyẹ náà dínkù dáradára, èyí si fún àwọn ènìyàn ni ànfàni láti lówó lọ́wọ́ ti wọ́n le ná.
Sùgbọ́n àwọn tọ jẹ́ pé, olá ìjọba ni wọ́n fi n mí, àti àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba, ìdẹnukọlẹ̀ ètò ọ̀rọ̀ ajé pa wọ́n lára gidi ni.














