Ọwọ́ tẹ̀ Abubakar tó wà ní JSS 3 lẹ́yìn tó jí ọmọ ọdún mẹrin ìbátan rẹ̀ gbé ní Katsina

Oríṣun àwòrán, @Others
Ariwo nibo ni ile aye n lọ ni o gba ẹnu ọpọ kan ni kete ti iroyin yii jade.
Ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria ni ipinle Katsina lo fi sita pe ọwọ ti tẹ ọmọdekunrin ẹni ọdun mẹrindinlogun kan nibẹ.
Abubakar Abdulbashir ni wọn kede pe o wa ni ipele iwe kẹta JSS 3 ti giram ni Katsina.
Oun ni won lo ji aburo rẹ nidi iya, Halima to jẹ ẹni ọdun mẹrin pere gbe to si tun n beere fun owo itanran ẹgbẹrun lọna aadọrin naira ni ilu Marabar Kankara ni ijoba ibile Malumfashi ni Katsina.
Won ni leyin to ji ibatan rẹ ẹni odun merin naa gbe tan lo lọ fi pamọ sinu ile akópati ni Marabar Kankara to si n pe fun owo itanran bi gbogbo ẹbi ṣe n daamu lati wa ọmọdebinrin naa kiri.
- Iléeṣẹ́ ológun Nàìjíríà sẹku pa àwọn jàndùkú nínú igbó Kaduna, wo nkan tí wọn rí gbà lọ́wọ́ wọn
- Ẹ yàgò fún àwọn olóṣèlú fẹ́rànjẹ̀kọ́ – Jonathan
- N30 mílíọ̀nù ní wọ́n ṣèlérí láti fún mi tí mo bá ri orí òkù kan gbé ní Ondo- Afurasi sọ fún Amotekun
- Àwọn afurasí agbébọn ṣekú pa èèyàn mẹ́tàlá ní ìpínlè Taraba
- Kìí ṣe gbájúẹ̀ nìkan lọmọ Nàìjá ń ṣe lókè òkun!
- Ǹkan ti ọlọ́pàá sọ rèé lórí ìjà Fulani àti OPC tó mú ẹ̀mí èèyàn mẹ́rin lọ ní Kwara
Bawo ni ọwọ agbofinro se tẹ Abubakar?
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Katsina salaye pe obinrin kan ni Olorun lo ti asiri fi tu.
wọn ni obinrin naa sakiyesi pe nise ni ọmọdebinrin ti Bashir ji gbe naa n sunkun ninu ile akopati naa eyi to mu ki oun ya sibẹ beere ohun to sele.
O ni pe Bashir so pe awon kan jọ n sere nile akópati naa ni.
Eyi lo mu ifura dani ti oun si lọ sile lọ pe baba re wa ti won si ke si awon agbofinro to wa nitosi ile akopati naa.
- Wo àwọn nọ́mbà ìpè agbófinró tó yẹ kò mọ̀, èyí tó pè tí ìkọlù agbébọn bá dé
- Òṣèré tíátà, ẹ má jẹ́ kí àbùkù wọ ìlàkàkà yín láti kó ọrọ̀ jọ - Ajirebi
- 'Láti ojú orun, ohùn kan máa ń tọ́ka ewé àti ègbòogi sí mi, báyìí la ṣe ń ṣe agbo fún ǹkan ọmọ ọkùnrin'
- Bàbá Orlando Owoh ti lọ kí n tó bẹ̀rẹ̀ sí ní lo ohùn orin wọn fi ṣe oríire láyé - Orlando Ore
- 'Ó yẹ kí ẹnu mi wọ́ sẹ́gbẹ̀ẹ́, kí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ má dá, mi ò lè rìn dáadáa'! Ṣé o lè mọ̀ lára Anifa pé ó ní Hemiplegia Cerebra
Leyin ti ọwọ agbofinro tẹ Obi Bashir ni oun naa ṣẹṣẹ wa yọju si agọ ọlọpaa lati fi ara rẹ han nigbẹyin.
O jẹwo pe tootọ ni oun ji Halima ọmọ aburo iya oun gbe.
Ati pe nitootó ni oun fi Halima pamọ si ile akóti nibi ti oun ti n beere N70, 000 naira owo itanran lọwọ obi Halima ibatan rẹ.
Bashir ni kete ti oun pe won tan pe ki wọn wa owo itanran naa lo ni eri ọkan bẹrẹ si ni jẹ oun ni eyi to si lodi si ẹsin Islam ti oun gbagbọ ninu rẹ.
O n beere fun idariji ẹṣẹ rẹ bayii pe ki awọn Obi Halima gba pe oun ti ronupiwada lori aṣise oun.
Kini ọlọpaa sọ lori iṣẹlẹ yii?
Agbenuso ileeṣẹ ọlọpaa Katsina, SP Isah Gambo salaye pe lootọ ni iṣẹlẹ naa.
Ati pe arakunrin Sanusi Abubakar to jẹ baba Halima ti wa fẹjọ sun ni agọ ọlọpaa lati igab ti o ti n daamu wa ọmọ rẹ kiri.
O ni nitootọ lo gba ipe lati san N70, 000 owo itanran ti ko ba fẹ ki wọn pa ọmọ rẹ, Halimatu Sanusi.
- Wàhálà míì tún bẹ́ sílẹ̀ láàrin ọmọ ẹgbẹ́ Shitte àti ikọ̀ aláàbò
- 'Uncle' mi fi ipá bámi lòpọ̀ lọ́mọ ọdún 15, ó sì di oyún - Toyin Lawani
- Wo ohun mánigbàgbé tí yóò wáyé níbi ọdún Osun Osogbo lọdún yìí
- Israel dáwọ́ ìkọlù sí Gaza dúró lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta
- Wo ojú àwọn jàndùkú afẹ̀mí-ṣòfò tó ń hùwà tani-ó-múmi ní àríwá Nàìjíríà
Agbenusọ ọlọpaa ni kete ti wọn kẹfin ibi ti ọrọ naa n lọ ni wọn ti bẹrẹ iṣẹ to jẹ ki owọ wọn tẹ Abubakar Abdulbashir to jẹ afurasi ibatan Halima Sanusi.
Bakan naa ni o fidie mulẹ pe afursai naa ti jẹwọ ẹṣẹ rẹ, igbesẹ to yẹ si ti bẹrẹ labẹ ofin.
- Kò rọrùn rárá láti dàgbà ní agbègbè bíi Mushin, àànú Ọlọ́hun ló sọ mi di agbábọ́ọ̀lù Super Falcons - Rasheedat Ajibade
- Ọkọ àfẹ́sọ́nà kọ̀ mí sílẹ̀ pé mo ní iṣan lápá, ọ̀yan mi sì ǹ rá torí iṣẹ́ ọ̀gbìn – Àgbẹ̀ Obìnrin
- Egungun Oloolu ti ilẹ̀ Ibadan fojú han aráyé! Gbọ́ àwọn ǹkan tó ń dẹ́rù ba obìnrin, ọmọde nípa rẹ̀ àti èèwọ̀ rẹ̀
- Bàbá Orlando Owoh ti lọ kí n tó bẹ̀rẹ̀ sí ní lo ohùn orin wọn fi ṣe oríire láyé - Orlando Ore
- Òṣèré tíátà, ẹ má jẹ́ kí àbùkù wọ ìlàkàkà yín láti kó ọrọ̀ jọ - Ajirebi

Oríṣun àwòrán, @Amotekun
N30 mílíọ̀nù ní wọ́n ṣèlérí láti fún mi tí mo bá ri orí òkù kan gbé ní Ondo- Afurasi sọ fún Amotekun
Owọ ikọ Ondo State Network Agency, ti ọpọ mọ si Amotekun ti tẹ arakunrin afurasi kan ti orukọ rẹ n jẹ Timothy Odeniyi.
Timothy Odeniyi to jẹ ẹni ọdun marundinlogoji ni ọwọ tẹ pẹlu ẹya ara ẹsẹ ati ọwọ oku ni ipinle Ondo.
Odeniyi salaye fun awon Amotekun pe ipinlẹ Eko ni onibara oun wa to n beere fun eya ara oku naa.
Lọjọ Aje ni wọn safihan ọkunrin naa to jẹwọ pe oun ge ẹsẹ ati ọwọ oku kan ni iboji agbegbe Sabo ni ilu Ondo nibi to sunmo olu ileese ijoba ibile Ondo West ni ipinle Ondo.
- Wo àwọn nọ́mbà ìpè agbófinró tó yẹ kò mọ̀, èyí tó pè tí ìkọlù agbébọn bá dé
- Àwọn aya Yekeen Ajileye ló fa ìpinyà láàrin wa débi pé mo fẹ́ pa ara mi - Abija
- 'Láti ojú orun, ohùn kan máa ń tọ́ka ewé àti ègbòogi sí mi, báyìí la ṣe ń ṣe agbo fún ǹkan ọmọ ọkùnrin'
- Bàbà ọmọ ọdún 75 kó HIV ran ọmọ ọdún 14 lẹ́yìn tó fi ipá báa lò
- Gbogbo ọjà di títì pa nílùú Akure, ṣugbọ́n nítorí kí ni?
Ọwọ ikó Amọtẹkun Ondo ló tẹ Timothy Odeniyi lẹyin tó ti ge ẹsẹ àti ọwọ oku kan ni itẹ́.
Timothy Odeniyi ti ọwọ tẹ yii lo sọ pe oun n sisẹ gẹgẹ bi awakọ ajagbe pelu ileeṣẹ to n po ọti ta kan tẹlẹ.
O ni ọga agba fun oun lasiko ti oun n siṣẹ nibẹ lo ran oun niṣẹ ẹya ara oku yii.
Timothy ni pe: Oga mi fẹ lo eya ara naa fun oogun owo ni
Lẹyin ti mo ti ge ọwọ ati ẹsẹ oku yii tan ni mo pinnu lati lọ gbe e fun eni to ran mi ki ọwọ to tẹ mi lẹyin ti mo jade kuro niboji oku naa.
Oga mi sọ pe ọgbọn miliọnu ni owo iṣẹ mi ni kete ti mo ba ti ko awọn ẹya ara naa de ọdọ rẹ.
- Iléeṣẹ́ ológun Nàìjíríà sẹku pa àwọn jàndùkú nínú igbó Kaduna, wo nkan tí wọn rí gbà lọ́wọ́ wọn
- Kìí ṣe gbájúẹ̀ nìkan lọmọ Nàìjá ń ṣe lókè òkun!
- Àsìkò tí tó fún àwọn ọ̀dọ́ láti gbá ìṣàkóso orílẹ̀èdè Nàìjíríà- Peter Obi
- Wò ó bí èsì ìbò ààrẹ ní Kenya ṣe lọ
- Ọwọ́ àwọn agbófinró Abuja tẹ afurasí 480 tó sá kúró lọ́gbà ẹ̀wọ́n Kuje
- Ẹgbẹ́ NLC kọ lẹ́tà sí Buhari pé kó fi ìdá àádọ́ta 50% kún owó oṣù òṣìṣẹ́ Nàìjíríà
Bakan naa ni afurasi yii salaye fun awọn Amotekun pe oun ko pa enikẹni ati pe igba akọkọ re e ti oun a ji ẹya ara oku ta.
Oga agba iko amotekun Ondo, Akogun Adetunji Adeleye sọ pe irọ ni afurasi naa n pa pe ko pa eeyan.
O ni pe ọwọ tẹẹ pẹlu ẹṣe ati apa eeyan to ti fi pépà we ni.
Ati pe léyin ti iya jẹ afurasi naa daadaa lo wa mu won lọ si ibi ti ara oku naa to ṣẹku ṣi wa ninu iboji kan ti ko jin rara ni agbegbe naa.
o ni pe iṣẹ n lọ lọwọ lati fa afurasi naa le agbofinro lọwọ fun igbese to kan















