Nigeria population: Buhari tako ọmọ bẹẹrẹ òṣì bẹẹrẹ ní Nàìjíríà, ó ṣàgbékalẹ̀ ètò láti dẹ́kun rẹ̀

Oríṣun àwòrán, Muhammadu Buhari
Aarẹ Muhammadu Buhari ti ṣe agbekalẹ eto ti yoo ṣe adinku ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ lorilẹede Naijiria.
Buhari to ṣe agbekalẹ eto naa niluu Abuja sọ pe o ṣe pataki bayii lati mu ifeto sọmọ bibi lọkunkundun.
Buhari tun ṣe agbekalẹ eto mii ti yoo ṣe iranwọ lori ati dẹkun bi awọn eeyan ṣe n pọ sii ni Naijiria.
- Ilé ẹjọ́ ju ọmọkùnrin mẹ́rin tó fi olólùfẹ́ ọ̀kan lára wọn ṣe òògùn owó sí ẹ̀wọ̀n
- Òbí ti kùnà nínú ojúṣe, à ń kó àwọn ọmọ yìí lọ sílé ẹjọ́- Oga Ọlọpàá Abimbola Oyeyemi
- Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ mẹ́rin tó fi Rofia ṣòògùn owó ti sùnlọ níbi tí wọ́n ti n jó orí rẹ- Olóri fijilante Abeokuta
- Àwọn ọmọ ogun America pa olórí ISIS, Ibrahim al-Qurayshi ní Syria
- Èèyàn 26 kú nígbà tí wáyà iná já lé wọn lórí láàrin ọjà
- Ọ̀gá àgbà NSCDC dá àwọn ẹ̀ṣọ́ àjọ náà tó wà pẹ̀lú Shina Peller padà
- Ìjọba Kano fẹ̀sùn oníkókó márùn ún kan àwọn afurasí tó pa ọmọ ọdún márùn ún Hanifa
Buhari ṣe agbekalẹ eto ifeto sọmọ bibi
Aarẹ Buhari ṣalaye pe ohun to bi eto ifeto sọmọ bibi wa ni lati mu ibayegbadun ba awọn ọmọ Naijiria.
Buhari ni eyi wa lara awọn eto ijọba ẹgbẹ oṣelu APC to wa lode bayii.
Eto yii yoo ṣe iranwọ lori bi adinku yoo ṣe ba bi ọpọ eeyan ṣe n bi ọmọ silẹ lọpọ yanturu.
Ara awọn ọna ti ijọba fẹ gba lati ṣe eto ọhun ni nipa ilanilọyẹ lori ifeto sọmọ bibi.
Aarẹ Buhari gbagbọ pe eto yii yoo ran ọpọ eeyan lọwọ lati fi alafao si aarin awọn ọmọ wọn.
Buhari kọminu lori bi Naijiria ṣe pọ julọ l'Afrika
Aarẹ Buhari ni orilẹede naijiria lo pọ julọ nilẹ Afirika nigba to tun jẹ orilẹede to wa ni ipo keje lagbaye.
Buhari ni Naijiria wa lara awọn orilẹede diẹ lagbaaye to ni ọdọ julọ.
Aarẹ ni ida mejilelaadọrin ninu ọgọrun awọn ọdọ yii ni ọjọ ori wọn ko to ọgbọn ọdun.
Bakan naa ni Buhari sọ pe idaji awọn obinrin ninu awọn ọdọ yii lo wa ni asiko ti wọn ṣe abiamọ tori ọjọ ori bẹrẹ lati ọdun mẹẹdogun si ọdun mọkadinlaadọta.
- Àbúrò mi dágbéré pé òun fẹ́ dé ibì kan, ìròyìn ikú rẹ̀ ni mo gbọ́
- Abdulsalami ní kò sẹ́ni tó pa MKO Abiola, àìsàn ló pa á, ẹbí Abiola yarí
- Orílẹ̀-èdè North Korea ṣe ìfilọ́lẹ̀ àdó olóró tó tóbi jùlọ láti ọdún 2017
- Ìdí rèé tí Yahaya Bello fi gbọdọ̀ dá Amotekun sílẹ̀ ní Kogi- Gani Adams
- Wo àwọn ìgbéyàwó tí ayé pariwo wọ́n lọ́dún tó lọ
- Àjọ SERAP gbé Ààrẹ Buhari lọ sílé ẹjọ́ nítorì kò wádìí N3B tó pòórá níléèṣẹ̀ ètò ẹ̀náwó
Ọna abayọ si ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ
Buhari ni ijọba ko ni dẹkun lilo eto ẹkọ to peye lati maa la awọn eeyan lọyẹ.
Aarẹ ni eto ẹkọ yoo ṣe iranwọ papaa julọ fawọn obinrin to ba jẹ ọmọde tori awọn ni wọn le gboyun nigba kugba.
Buhari tun sọ pe eto ikaniyan to n bọ yoo tun ṣe iranwọ lati mọ ọna lati mu adinku ba ọmọ bẹẹrẹ oṣi bẹẹrẹ.
Ni bayii, akọsilẹ fihan pe eeyan to wa ni Naijiria le ni ẹgbẹrun lọna igba eleyii yoo si tun pọ sii lọjọ iwaju.

















