Baba Ijesha: Iyabo Ojo ní òun kò tíi jámi lórí ọ̀rọ̀ ọmọ Princess, òun ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni

Oríṣun àwòrán, other
"Mo maa n roo tẹlẹ pe ijaba ni iṣoro orilẹede yii ti a n pe ni Naijiria ṣugbọn mo ti rii pe awa ara wa gan an ni iṣoro ara wa."
Ọrọ ti gbajumọ oṣere, Iyabọ Ojo fi bẹrẹ ninu fidio kan to n ja ranyinranyin lori ayelujara ree ninu eyi to ti n fi iha to kọ si beeli ti wọn fun Baba Ijẹṣa han.
Baba Ijesha ni eekan oṣere ti awọn ọlọpaa fi si ahamọ lori ẹsun iwa aṣemaṣe pẹlu majesin, tii se ọmọdebinrin adẹrinposonu nni, Princess.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Baba Ijesha gba béélì níléẹjọ́ Májísírétì, àmọ́ ọ̀rọ̀ kù kó tó jáde l’àhámọ́
- Sunday Igboho lọ sọ́dọ̀ Guru Maharaji lórí ìdásílẹ̀ Yoruba Nation
- "Sunday Igboho kò fí lààkáyé kún ìjìjàgbara rẹ̀ nípa àtakò sí ìbò 2023"
- Mò ń wá olè tó jí nńkan ní ọọ́físì mi, ẹ̀bùn owó iyebíye rèé - Afeez Eniola
- Ohun tó ṣẹlẹ̀ ní ìlú Modakeke àti Ile Ife
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni Baba Ijesha ti jáde ní àhámọ́ ọlọ́pàá?
- Ìròyìn òfegè táwọn èèyàn ń gbé kiri lórí ìjà Israel àti Palestine rèé
- Ohun tí àwon Gómìnà egbẹ́ òsèlú PDP fenukò lé lórí rèé nílùú Ibadan
- Nǹkan dé o! Àwọn àgbébọn tún yìnbọn pa ọlọ́pàá méjì lẹ́nu iṣẹ́, wọ́n dáná sun àgọ́ ọlọ́pàá
Ni ọjọ Aje, ọjọ kẹtadinlogun oṣu karun un ọdun 2021 ni adajọ Majisireeti agba kan ṣilẹkun anfani beeli silẹ fun Baba Ijẹṣa lori ọrọ ailera ara rẹ.
Iyabọ Ojo ni o fihan gbangba pe ọpọ ọmọ orilẹede Naijiria ni iwa imọtaraẹnikan ni ironu wọn. Eyi lo si faa ti ọpọ maa fi n de ijọba ti iwa kiko ọrọ ilu si ikawọ arawọn.
O ni oun ko ti jami lori ọrọ ọmọdebinrin ti wọn fẹsun kan baba Ijẹṣa pe o ṣe aṣemaṣe pẹlu.
O fi kun pe bi ọpọ ba ri ohun to ṣẹlẹ si ọmọdebinrin naa gẹgẹ bi eyi ti ko kan wọn









