Yoruba Nation: Àbọ̀ tí Sunday Igboho mú bọ̀ rèé lẹ́nu àbẹ̀wò rẹ̀ sọ́dọ̀ Guru Maharaji

Oríṣun àwòrán, Screen Shot
Ajijagbara fun idasilẹ́ orilẹede Yoruba, Oloye Sunday Igboho ti se abẹwo sọdọ asaaju ẹsin One Love Family, Sat Guru Maharaji nilu Ibadan.
Igboho, ẹni to ko ọpọ awọn ajijagbara sodi lọ sile asaaju ẹsin naa to wa loju ọna marosẹ Ibadan silu Eko, ni ko si ẹni to mọ idi to fi lọ.
Amọ fidio kan to n ja rain lori ayelujara lo safihan Igboho to n kan saara si Maharaji fun atilẹyin rẹ lori ipe fun idasilẹ orilẹede Yoruba.
- "Sunday Igboho kò fí lààkáyé kún ìjìjàgbara rẹ̀ nípa àtakò sí ìbò 2023"
- Kábíyèsí Ooni ti forí jin Sunday Igboho lẹ́yìn tó túúbá- Ààfin Ile Ife
- Akintoye sá lọ Amẹrika lásìkò ìjọba ológun, ó wá fẹ́ da Naijiria rú báyìí - Akeredolu
- Bí Buhari kò bá ṣọ́ra, àwọn ọba alayé ni yóò ṣaájú ìjìjàgbara fún Yorùbá - Sunday Igboho
- Sunday Igboho yarí, ó fohùn ránsẹ́ sáwọn èèyàn tó ń pẹ̀gàn rẹ̀
- A ti ṣetán láti fi ẹ̀mí wa lélẹ̀ fún òmìnira ilẹ̀ Yoruba, a ò níbi kankan ti a fẹ́ sálọ - Ọba Adetokunbo Tejuosoho
- Lọ́ọ̀tọ́ ní Sunday Igboho wá sí igbó Ire-Ekiti láti bọ Ogun lákáyé!- Akọ̀wé ìpínlẹ̀ Ekiti
Bakan naa lo n rọ asaaju ẹsin naa lati kede atilẹyin rẹ nita gbangba fun ominira orilẹede Yoruba nitori o ni awọn gbadun bo se dugba gbogbo nnkan tawọn n se.
Nigba to n fesi, Sat Guru Maharaji ni atẹlẹwọ ẹni kii tan ni jẹ, ati pe gbogbo awọn orisa wa, omi , odo, Oluwo, Apena atawọn Ọba wa mọ pe oun duro ti Sunday Igboho.
"Gbogbo awọn igbesẹ to n gbe pe ki iran Yoruba ma subu tabi parẹ, o si da mi loju pe gbogbo orisa ilẹ Yoruba lo duro ti Igboho.
Bi o si se n lọ ni yoo se ohun to yẹ ko se ti ko fi ni si wahala mọ nitori awọn to wa niwaju gan, o ti rẹ wọn."
O wa rọ awọn akẹkọọ ati gbogbo araalu lati duro ti Igboho, ki wọn si duro lori otitọ, ka le gba Naijiria la, amọ ti ko ba ri bẹẹ, a jẹ pe oduduwa ti duro niyẹn.
Guru Maharaji ni "a ko binu tabi ba ẹnikẹni ja amọ a ko le duro sile ki ebi maa pa wa, ka wa ro pe o digba ta ba de ọrun, ki ara to tu wa, rara, a gbọdọ gba ara wa la.."
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Baba Ijesha gba béélì níléẹjọ́ Májísírétì, àmọ́ ọ̀rọ̀ kù kó tó jáde l’àhámọ́
- "Sunday Igboho kò fí lààkáyé kún ìjìjàgbara rẹ̀ nípa àtakò sí ìbò 2023"
- Mò ń wá olè tó jí nńkan ní ọọ́físì mi, ẹ̀bùn owó iyebíye rèé - Afeez Eniola
- Ohun tó ṣẹlẹ̀ ní ìlú Modakeke àti Ile Ife
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni Baba Ijesha ti jáde ní àhámọ́ ọlọ́pàá?
- Ìròyìn òfegè táwọn èèyàn ń gbé kiri lórí ìjà Israel àti Palestine rèé
- Ohun tí àwon Gómìnà egbẹ́ òsèlú PDP fenukò lé lórí rèé nílùú Ibadan
- Nǹkan dé o! Àwọn àgbébọn tún yìnbọn pa ọlọ́pàá méjì lẹ́nu iṣẹ́, wọ́n dáná sun àgọ́ ọlọ́pàá
Asaaju ẹsin naa wa kesi awọn gomina nilẹ Yoruba lati maa tọju awọn eeyan to n jija gbara fun ilẹ Yoruba, o ni ko yẹ ki wọn sa gbogbo nnkan si oorun.
"Ẹ fun wọn ni mọto, bi wọn se n se ni Amẹrika, Japan nuu. Ti wọn ba ri olotitọ, wọn maa n duro ti wọn ni, ẹru ko gbọdọ ba yin. Oduduwa ti de o."





















