Sunday Igboho: Ẹ gbàgbé Gẹ̀ẹ́sì, ọpọlọ mi pé ju tàwọn tó kàwé lọ

Ooni, Sunday Igboho ati Alaafin

Oríṣun àwòrán, Ooni, Sunday Igboho ati Alaafin

Ilumọọka ajafẹtọ iran Yoruba, Oloye Sunday Igboho, tun ti yọ suti ete sawọn eeyan to n kẹgan rẹ pe ko kawe debi to ni apẹrẹ.

Sunday Igboho, lasiko to n bawọn ololufẹ rẹ sọrọ lọjọ Aiku lo fesi pada fawọn ọmọ Yoruba to ni ko kawe to nnkan.

Igboho ni awọn ọmọ Yoruba kan lo n kẹgan oun pe oun ko yẹ ni ẹni ti yoo lewaju iran Yoruba nidi ijijagbara nitori pe oun ko gbọ ede oyinbo bo se yẹ.

Sunday Igboho

Oríṣun àwòrán, Instagram/Sunday Igboho

Igboho ni "Wọn ni n ko kawe, ti n ko si le ja fun iran Yoruba, amọ alaimskan ni wọn, ti ko ni laakaye."

Ajafẹtọ ọmọniyan naa ni ọpọlọ toun ju tawọn eeyan to n pẹgan oun lọ, bi o tilẹ jẹ pe oun ko kawe to wọn.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Igboho ni ilẹ Yoruba ni oun n ja fun, ko si si ohun to kan ohun ninu sisọ ede Gẹẹsi nitori bi aarẹ Amẹrika yoo ba ba oun sọrọ, ede abinibi oun ni oun yoo fi baa sọrọ.

Asiko yii lo si bẹrẹ si ni sọ ede Gẹẹsi, tawọn alatilẹyin rẹ si n sa ni mẹsan-mẹwa.

Àkọlé fídíò, Sunday Igboho: Fulani kò leè dúró, táa bá lo ohun ta jogún lọ́dọ̀ àwọ̀n bàbá wa

"Ko si ohunkohun ti mo fẹ gba lọwọ ẹni to pe ara rẹ ni ọjọgbọn fasiti, nitori gbogbo awọn ti wọn ni awọn gbọ eebo yii, iru wọn lo n se isẹ asọna lẹnu ọna ile mi."

"Ila ẹẹkẹ mi ni iwe ẹri pe mo jẹ ojulowo ọmọ Yoruba ti ko ni abula, ti ilẹ Yoruba ba si ni ominira tan, ede abinibi la mu lskunkundun.

Ede oyinbo ti wsn n gbe larugẹ yoo si jẹntẹdi, eyi ti ko ni wulo mọ rara."

N ko jẹ Aarẹ Ọna Kakanfo, ko si ohun ti mo fẹ fi se

Bakan naa ninu ifọrọwerọ ọhun ni oloye Sunday Igboho tun ti sisọ loju rẹ pe oun ko ni lero rara lati jẹ Aarẹ Ọna Kakanfo nilẹ Yoruba.

Igboho salaye pe oye to ga julọ, ti gbogbo agbaye fi mọ oun ni Igboho, Ọlọrun Ọba si lo fun oun.

Àkọlé fídíò, Adebunmi Adeyeye: Mo jẹ gbèsè gbọ́múléláńtà, ìdí iṣẹ́ kabúkabú ni mo ti ri san

"Ko si oye tẹ le fun mi laye yii, lai pe Igboho mọ, aye ko le mọ pe emi lẹ n sọrọ rẹ.

N ko nilo oye aarẹ ọna kakanfo kankan mọ lẹyin Igboho ti Ọlọrun fun mi."

Awọn ọba alaye setan lati siwaju ogun fun ijijagbara ilẹ Yoruba

Sunday Igboho tun ti fidi rẹ mulẹ pe awọn ọba alaye ilẹ Yoruba ti wa lẹyin oun gbaa gbaa gbaa nidi ijijagbara fun ilẹ Yoruba.

Igboho ni "Iku Baba Yeye, alasẹ ekeji orisa lo n sọrọ lọwọ bi mo se n sọrọ yii, nitori o wa pẹlu wa.

Koda, Oonirisa Ọjaja Adeyeye Enitan Ogunwusi gan wa pẹlu wa, to fi mọ Awujale, Olugbon, Olu Ilaro atawọn ọba yoku ni agbegbe Oke Ogun to fi mọ Olukere.

Àkọlé fídíò, Akomolede àti Asa: Mọ̀ si nípa àṣà ìsọmọlórúkọ́ nílẹ̀ Yorùbá àti ìtumọ̀ orúkọ̀ fún ìkókó

Igboho ni awọn ọba alaye naa ti n sọ fun aarẹ Muhammadu Buhari pe ti ko ba sọra, o seese ko jẹ awọn ọba ilẹ Yoruba ni yoo siwaju ijijagbara yii gkgẹ bo se waye laye atijs ti ọba maa n siwaju ogun.

"Koda, gbogbo awọn kabiyesi ti kọ lẹta si Buhari lori ọrọ awọn apaayan Fulani pe funra awọn ni awọn yoo sigun, eyi to fi skan wa balẹ pe a ni baba to n ti wa lẹyin.'

Ọwọ́ mi dẹ púpọ̀ ní Ayete, n kò kéde lórí ayélujára ní - Sunday Igboho

Sunday Adeniyi Adeyemo Igboho

Oríṣun àwòrán, Sunday Igboho/Instagram

Ilumọọka ajijagbara ọmọ Yoruba nni, Oloye Sunday Adeyemo, ti ọpọ eeyan mọ si Sunday Igboho, tun ti salaye lori bi irinajo rẹ silu Ayete lọjọru to kọja se ri.

Igboho, lasiko to n bawọn ọmọlẹyin rẹ atawọn araalu sọrọ lori ayelujara lọjọ Aiku lo ti salaye nipa irinajo rẹ ọhun.

Igboho ni " irinajo mi silu Ayete so eso rere pupọ, ti ọwọ oun si dẹ nidi sise awari awọn afurasi ọdaran darandaran amọ mo kọ lati kọkọ gbe sori ayelujara ni.

Awọn agbaagba Yoruba ti ba wa wi pe eeyan kii fi gbogbo ẹnu sọrọ, gbogbo asọ kọ la a saa loorun, a si ti gbọ, tori naa ni n ko se kọkọ gbe fidio sita nigba ti mo n lọ."

Àkọlé fídíò, Sunday Igboho: Ẹ fi Ògún búra fún wa láti jà fún ilẹ̀ Yorùbá láì gbé Amotekun sábẹ́ ìjọba

Igba ti Yoruba ba de ilẹ ileri, ti alaafia jọba ni maa to sinmi ijijagbara

O fikun pe diẹ ni fidio ati iroyin tawọn araalu gbọ nipa irinajo naa, kii si se gbogbo ohun ti oun ba n se, ni oun yoo maa gbe sori ayelujara mọ.

Igboho ni nigba toun di ilu Ayete de, ni oun to se fidio sita nipa awọn isẹ ribiribi ti oun se lati pe alaafia pada silu naa.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

"Fidio ti mo gbe diẹ sita nipa ohun ta se nilu Ayete ni yoo jẹ kawọn eeyan mọ pe kii se ẹnu lasan ni oun fi n se ijijagbara fun ilẹ Yoruba, tabi pe a ti lọ sinmi tabi jami lori rẹ."

Sunday Igboho ni o di igba ti iran Yoruba ba de ilẹ ileri, toun ri pe alaafia ti wa, ki oun to sinmi nidi ijijagbara naa.

Mo n jẹ mọsa ọrọ Fulani ni eteeti lọwọ ni, n ko tii bo loju gan

Bakan naa lo ni oun si n jẹ mọsa ọrọ awọn ọdaran Fulani ni eteeti lọwọ ni, oun ko tii bo loju gangan amọ laipẹ ni oun yoo bo loju torotoro, ti Yoruba yoo si de ilẹ ileri.

Ajijagbara ọmọ ilẹ Yoruba naa wa fi ọwọ sọya pe awọn ọdọ tawọn n jija gbara fun ilẹ Yoruba lasiko yii, ni yoo gba ominira fun ilẹ Yoruba, kii si se iran to n bọ.

"Awọn ọmọ wa kọ ni yoo gba ominira fun iran Yoruba, awa ọdọ yii ni. Ẹ gbagbe pe a se aseti lori rẹ, ta si gbe le awọn ọmọ wa lọwọ.

Àkọlé fídíò, Adebunmi Adeyeye: Mo jẹ gbèsè gbọ́múléláńtà, ìdí iṣẹ́ kabúkabú ni mo ti ri san

Ọlọrun lo ti mi sita lati wa sisẹ yii, ko si oun ti mo fẹ, ti Ọlọrun ko fun mi, ko si yẹ ko jẹ iru emi ni yoo ma sisẹ ijijagbara yii, amọ Ọlọrun lo ran mi."

Yoruba, ẹ fun sokoto yin ko le, a ko boju wẹyin mọ

Ninu eto ibanisọrọ naa ni Igboho tun ti kesi awọn ọmọ Yoruba lati fun sokoto wọn ko le, nitori ko si ọrọ pe a n boju wẹyin mọ.

O fikun pe ko si ohunkohun kankan to le dun mọhurumshuru mọ wa mọ.

Àkọlé fídíò, Prophet Shittu Adeniyi: Ẹni tó bá ń tọrọ agbe, kìí jẹ́ èèyàn ní mo ṣe tẹ́pa mọ́ṣẹ́

"Sheik Gumi mọ ibi ti awọn ajinigbe agbebọn wa, to si n beere pe ki ijọba darijin wọn. Amọ awa ta n fẹ alaafia fun Yoruba lẹ n ko, tẹ fẹ gbe sahamọ, ko le seese.Yoruba, ẹ fun sokoto yin ko le, a ko boju wẹyin mọ