Rape of minors: Ẹni bá rí i kó sọ o, Ìjọba ń wá ẹni dún 45 tó fipá bá ọmọ ọdún méje lòpọ̀

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ile aṣofin nipinlẹ Bauchi ti gbe igbimọ dide lati ṣawari ọkunrin ẹni ọdun marundinlaadọta to fi ipa ba ọmọ ọdun meje lopọ.
Awọn aṣofin kan ni ileeṣẹ ọlọpaa ti gba beeli ọkunrin naa lẹyin ti wọn fi panpẹ ọba gbe.
Agbegbe ijọba ibilẹ Faggo ni Shira ni iṣẹlẹ naa ti waye.
- Olùkọ́ mi ń bá mi lòpọ̀ kí ń le yege ìdánwò WAEC - Akẹ́kọ̀ọ́ l‘Ogun
- Bàbá ọlọ́mọ méjì fi ipá bá ọmọ ọdún mẹ́rin lò pọ̀; Adájọ́ rán an ní ẹ̀wọ̀n gbére
- Afipábánilòpọ̀ méjì tún ṣọṣẹ́ lára ọmọ ọdún 17 l'Ekiti
- "Sọ́jà fi ìbọn gé mi lọ́wọ́ kó lè fipá bámi lòpọ̀"
- Inú mi dùn lórí òfin títẹ àwọn àfipábánilòpọ̀ ní ọ̀dá - Foluke Daramola
- Wo iye obìnrin lágbàáye tó ń kojú ìwà ipá, àti ohun tó ń ṣokùnfà ẹ̀?
Ọkan lara awọn aṣofin to gbe ọrọ naa ka ile aṣofin ni ki ileeṣẹ ọlọpaa ni kiakia wa ọkunrin yii jade lai fi akoko ṣofo.
O ni ọkunrin agbalagba naa ba ọmọbinrin naa lopọ lẹyin to dunkoko mọ ọ wi pe oun yoo pa a.
Bakan naa lo fi da awọn oniroyin loju wi pe awọn yoo ri wi pe ijọba fi ọkunrin oun jofin.
O ni awọn yoo ṣewadii ni ijọba ibilẹ Shira ati ileeṣẹ ọlọpaa ni agbegbe naa ibi ti wọn de duro lori bi wọn ṣe fi panpẹ ọba mu ọkunrin naa.
Amọ, nibayii awọn aṣofin naa ni awọn ko mọ ibi ti ọkunrin naa salọ, sugbọn awọn fi n da awọn araalu loju wi pe arakunrin oun ko ni lo lai jẹ iya ẹsẹ rẹ.
Ijọba ipinlẹ Bauchi ni ifipabanilọpọ ti wọpọ nipinlẹ naa, ti wọn si ti fi ofin de iru iwa bẹẹ ni ipinlẹ ọhun.
Ẹwọn ogun ni ijọba yoo fun ẹnikẹni ti wọn ba fi idi rẹ mulẹ pe o fi ipa ba obinrin lopọ.
- Ṣé lóòtọ́ ni Alaafin Ọyọ ti fẹ́ olorì tuntun láti ẹ̀yà Igbo? Ẹ wo ǹkan tí a mọ̀ nípa rẹ̀
- Wàwúù!!! Lẹ́yìn ọmọ márun-ùn, wo bí ìyàwó àgbẹ̀ se tún bí ìbaàrùn-ún ní Ogbomoso láì ṣe iṣẹ́ abẹ
- Torí Kashy Godson ni abúrò mi Barry Jhay ṣe lọ sí Ghana, kí lódé tó fi máa pa á? - Ronke Balogun
- Wọ́n jí mi gbé, só mí mọ́lẹ̀ bí ẹ̀ran, fipábámilòpọ̀ láti di aya wọn torí mo jẹ́ Krìstẹ́nì - Ọmọbìnrin ọdún méjìlà













