Florence Ajimobi: Àwọn Káfíńtà ti kó igi dé láti tún òrùlé ilé ìtajà tó jóná ṣe

Awọn agba ni ọjọ taa ba ri ibi, ni ibi n wọ ilẹ, ohun to ba si ti ya kan, kii tun pẹ ms.
Eyi lo mu ki aya gomina ana nipinlẹ Oyo, Florence Ajimobi tete pakiti mọlẹ lati se atunse ibudo itaja rẹ to jona.
Bẹẹ ba gbagbe, alẹ ana la mu iroyin wa fun yin pe abala kan lọwọ ẹyin ibudo itaja aya Ajimobi naa, Grandex, to wa ladugbo Bodija nilu Ibadan gbina.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ojúlówó Shina Rambo yọjú sígboro lọ́jọ́ Àìkú, ó fi ìka hánu lórí ìpànìyàn tó ti ṣe
- Ọmọ Nàìjíríà mẹ́fa tó n fi owó ránṣẹ́ sí Boko Haram rẹ́wọ̀n he ní Dubai
- Mọ̀ síi nípa Shina Rambo tó pàdé Jesu lọ́gbà ẹ̀wọn lẹ́yìn tó ti jalè
- Wàhálà míì dé! Nupeng àti Pengassan gùnlé ìyanṣẹ́lódì
- Làásìgbò ọ̀tun súyọ nínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC
- Báwo ni Joe Biden yóò ṣe mú ìyípadà bá òfin tí Trump fi de orílẹ̀èdè àgbáyé?
- Afurasí afipábánilópọ̀ kàgbákò, obìnrin tó jà lólè fi eyín gé nǹkan ọkùnrin rẹ̀ jábọ́ lásìkò ‘Blow Job’
- Àwọn ọba alayé, Mínísítà àti gómìnà nílẹ̀ Yorùbá ṣèpàdé pẹ̀lú ìjọba àpapọ̀, àbọ̀ rèé
- Iná ṣẹ́yọ nílé ìtajà aya Ajimobi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta tó jáde opó
Amọ nigba ti ikọ iroyin BBC se abẹwo sibudo itaja naa loni, a se akiyesi pe aayan ti n lọ lati se atunse abala ile itaja to jona naa.
Ikọ iroyin BBC Yoruba kofiri awọn Kafinta ti wọn ti ra igi da silẹ lati tun orule to jona kan, to si seese ki isẹ atunse naa bẹrẹ lọla.
Iná ṣẹ́yọ nílé ìtajà aya Ajimobi lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta tó jáde opó

Oríṣun àwòrán, oyoinsight.com
Saaju la ti sọ fun yin pe, ina nla kan ti ṣẹyọ to si ṣakoba fun ọpọ dukia ni ile itaja iyawo Gomina ipinlẹ Oyo tẹlẹ, arabinrin Florence Ajimobi.
Ile itaja igbalode taa n sọ yi ni Grandex Supermarket to wa ni agbegbe Bodija nilu Ibadan.
Iṣẹlẹ yi to se awọn eeyan ni haa, waye lẹyin ọjọ mẹta ti Arabinrin Florence jade ile opo iku ọkọ rẹ, Sẹnẹtọ Abiola Ajimobi .
- Ẹbí Abiola Ajimobi kéde bí ètò ìsìnkú rẹ̀ yóò ṣe rí pé...
- Ganduje àtàwọn èèkàn ìlú míì sàmì ogójì ọjọ́ tí Ajimobi dará ilẹ̀
- "Ìfẹ́ akọ sákọ àti abo sábo tó wọ́pọ̀ ní Àríwá Nàíjíríà ló fa ìbínú Ọlọ́run"
- 'Àìjáfáfá àwọn panápaná ló mú kí ọṣẹ́ iná Akure pọ̀'
- Ó ṣe jẹ́ ṣọ́ọ́bù aláṣọ kanṣoṣo ni iná tí maa ń ṣẹ́yọ lọdọọ́dún lọ́jà Balogun?
Awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn sọ pe ina naa ṣadede ṣẹyọ lọsan ọjọ Aiku lati ọwọ ẹyin ile itaja naa ti ko si pẹ to fi ran kaakiri.
Titi di igba ta fi n ṣe akojọ iroyin yi, a ko ti fidi ọrọ mulẹ lori ohun to fa ina naa.

Oríṣun àwòrán, @aishambuhari
Florence Ajimobi jáde ilé opó lẹ́yìn ọjọ́ 140 tí ọkọ rẹ̀ jáde láyé
Aya gomina ipinlẹ Oyo tẹlẹ, Abiola Ajimobi to ti di oloogbe bayii, Florence Ajimobi ti jade ile opo lẹyin ogoje ọjọ.
Abiola Ajimobi papoda lọjọ karundinlogun, oṣu Kẹfa, ọdun 2020 nile iwosan aladani kan nipinlẹ Eko, lẹyin to lugbadi arun Covid-19.
Lẹyin iku rẹ ni aya rẹ ọhun wọle opo ologoje ọjọ gẹgẹ bi ilana ẹsin Musulumiṣe gbe kalẹ.
- A kò ní gba ẹnikẹ́ni láàyè láti ṣe ìfẹ̀hónúhàn kankan mọ́ ní ìpínlẹ̀ Eko- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá kìlọ̀
- Wo ìgbà márùn ún tí Buhari ti rìnrin àjò lọ sókè òkun fún ìtọ́jú ara rẹ̀
- Mo ṣetán láti dojú ìjà kọ ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ bá ọ̀rọ̀ ajé Eko jẹ́- Sanwo Olu
- Sanwo-Olu buwọ́lu ìgbésẹ̀ ìjọba láti tún Eko ṣe lẹ́yìn rògbòdìyàn EndSARS
Nigba ti wọn n sọrọ lẹyin ti aya gomina tẹlẹri ọhun jade ile opo, ẹgbẹ awọn obinrin ninu ẹgbẹ oṣelu APC baa ṣajọyọ, wọn si tun kii ku oriire.

Oríṣun àwòrán, @vanguardngrnews
Ninu atẹjade ti awọn obininrin na fi lede, wọn ki aya Ajimobi ku irọju ati afarada lẹyin iku ọkọ rẹ.
- Bí àwọn kan tí ń ní àtimọ̀lé tí wọ́n sọ olorin Nazir sí ní Kano ni ọwọ́ kan òṣèlù ní àwọn mii ní...
- Afẹ́fẹ́ gáàsì tí gbiná ní Ijora ìpínlẹ̀ Eko, bó ṣe n ṣẹlẹ̀ rèé
- Ẹkún àti ìbànújẹ́ láwọn mọ̀lẹ́bí fi sìnkú ọmọ méje ní Kumba, Cameroon lónìí
- Ìdájọ́ ikú ló bá dé fáwọn méjì tó fipá bá ọmọ ọdún mẹ́rìnlá lò pọ̀
Atẹjade naa ti olori awọn obinrin ẹgbẹ APC ipinlẹ Oyo, Mabel Williams ati igbakeji rẹ, Toyin Ajibade buwọlu ki Florence Ajimobiu ku irọju.
Wọn ni "a ti gba f'Ọlọrun pe olori ati aṣiwaju wa ti dagbere faye, a si n fi akoko yii ṣeranti rẹ."
"A si fẹ fi akoko yii sọ fun aya olori wa, iyẹn, Florence Ajimobi pedigbi ni a wa lẹyin lọjọ gbogbo."
- Oṣú mẹ́fà ni òṣìṣẹ́ ìjọba tó bá bímọ yóò máa lò nílé kó tó wọṣẹ́ padà- Seyi Makinde
- Ọ̀rọ̀ ìjókòó ìgbìmọ̀ ìwádìí #EndSARS náà dé ìpínlẹ̀ Ogun
- ₦50 bílíọ́nù ni a pín fún gbogbo ìpínlẹ̀ ní Naijiria láti kojú àrùn Covid-19- Ìjọba àpapọ̀
- Ẹ fún wa lówó oṣù wa tàbí kí a gùnlé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ- Àwọn dokita ìpínlẹ̀ Ondo
















