Babajide Sanwo Olu, El Rufai: Mo ṣetán láti dojú ìjà kọ ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ bá ọ̀rọ̀ ajé Eko jẹ́- Sanwo Olu

Oríṣun àwòrán, @Lagosgovt
Mo ṣetán láti dojú ìjà kọ àwọn tó fẹ ba ọrọ ajé Èkó jẹ
Gomina Babajide Sanwo-Olu ipinlẹ Eko tí seleri lati koju gbogbo awọn to ba n gbero lati tẹ oju ọrọ aje Eko mọlẹ.
O fidi ọrọ yi mu'lẹ lasiko to n gba akẹgbẹ rẹ lati ipinlẹ Kaduna Nasir El-Rufai lalejo ni ile ìjọba.
- A kó ní sanwó oṣú ASUU láìjẹ́ pé wọ́n gba IPPIS- Ìjọba Àpapọ̀
- Ìdájọ́ ikú ló bá dé fáwọn méjì tó fipá bá ọmọ ọdún mẹ́rìnlá lò pọ̀
- Bí àwọn kan tí ń ní àtimọ̀lé tí wọ́n sọ olorin Nazir sí ní Kano ni ọwọ́ kan òṣèlù ní àwọn mii ní...
- Ẹkún àti ìbànújẹ́ láwọn mọ̀lẹ́bí fi sìnkú ọmọ méje ní Kumba, Cameroon lónìí
- Wo bí àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣe n kí fún ìjọba nítorí $1.2bn Naira tó fẹ́ ẹ yá lọ́wọ́ Brazil

Oríṣun àwòrán, @Lagos govt
Sanwo-Olu ni ijọba oun n wa gbogbo ọna ajọṣepọ ti yoo mu ki ipinlẹ Eko gberasọ padà.
Bakan naa lo salaye pe: ijọba ko ni yẹ lati ri pe ayé ko gba gbogbo awọn to ba fẹ ba eto ọrọ aje ipinlẹ naa jẹ.
O ni toun ti gbogbo rogbodiyan to tẹle iwọde ENDSARS oun ṣetan lati fidi idajọ ododo rinlẹ fun awọn to farakasa ijiya eyikeyi lọwọ àwọn ọmọ ikọ SARS

Oríṣun àwòrán, @Lagos govt
Ninu ọrọ tirẹ Gomina Kaduna Nasir El-Rufai ni omije fẹ lè máa bọ loju oun nigba toun ri akoba t'awọn janduku ṣe ni Èkó.
O ni ara wọn ni awọn to ba nkan ilu jẹ da loro ati pe bopẹ boya wọn yóò jèrè àkóbá ti won ṣe.
"A o ṣe gbogbo nkan ti ipinlẹ Eko ba nilo ká ṣé ni iranwọ lati le gbe Eko dide pada"

























