Ẹkún àti ìbànújẹ́ láwọn mọ̀lẹ́bí fi sìnkú ọmọ méje ní Kumba, Cameroon lónìí

Oríṣun àwòrán, Joel Kouam
Ẹkun oun ibanujẹ l'awọn molebi fi n sinku awọn ọmọ wọn meje to kagbako iku ni ilu Kumba lorile-ede Cameroon.
Ninu ibanujẹ yi naa ni wọn tun kesi ijọba lati fidajọ ododo mulẹ lori iku awọn ọmọ yi.
Lọjọ Kẹrinlelogun, oṣu Kẹwaa ni awọn agbebon ṣina bo'lẹ ti wọn pa ọmọdé meje t'awọn mejila miran si farapa ni ile ẹkọ Mother Francisca International Bilingual Academy, Fiango Kumba, ni iwọ oorun guusu
Cameroon.
- Ìgbónára ló máa ń mú àwọn èèyàn ṣe "Jungle justice" tí ìjàmbá ọkọ̀ bá ṣẹlẹ̀- Dokita
- Oṣú mẹ́fà ni òṣìṣẹ́ ìjọba tó bá bímọ yóò máa lò nílé kó tó wọṣẹ́ padà- Seyi Makinde
- A ti gbé ìwádìí dìde lórí ìpànìyàn tó wáyé lásìkò ìwọ́de EndSARS- Ilé ẹjọ́ àgbáyé, ICC
- Oyinkan Abayomi, akọni obìnrin tó fi ìfẹ́ pa orúkọ ọkọ kejì dà sí ti ọkọ àárọ̀
- Àlàyé rèé lóríi ìdí tí wọ́n fi ń pe aya ní ìyàwó
Ijọba orileede naa lo ṣeto isinku awọn ọmọ yi ti olootu ijọba Joseph Dion Ngute si soju Aarẹ Biya níbẹ.
Ṣaaju isinku lawọn mọlẹbi ke gbajare pe ki ijọba wadii awọn to sẹku pa awọn ọmọ wọn.
"Inu ibanujẹ la wa ni mọlẹbi mi,igba yi buru púpọ fún wa" ni oun ti Nzakame Julius sọ lasiko to n sin oku ọmọ rẹ Nzakame Rema to jẹ ọmọ ọdún mọkanla.

Oríṣun àwòrán, Joel Kouam
"Mo máa ṣe afẹri imoran ti Rema maa n gba mi pe ki n yago fun ọti mimu ki n si maa lọ si ile ijọsin deede.
Ọmọ yẹn jẹ olubẹru Ọlọrun. O mọ Ọlọrun ju mi lọ"
Pasitọ Victor Camibon naa to padanu ọmọ rẹ ni oun ko ni gbagbe bi "o ti ṣe maa n lu ilu ninu ijọ ti a si maa ba wa ṣi ferese ile ijọsin wa"

Oríṣun àwòrán, Evelyne Metuge
Ajọ ajafeto-omoniyan, Human Rights ti kesi ijọba Cameroon la ti ṣe iwadii tó tọ ki wọn si fi iya jẹ awọn to lọwọ ninu ipaniyan to waye ni Kumba.
Wọn fi kun un pe ki won gbe awọn akọṣẹmọṣẹ oniwadii wa lati UN ati AU ki ọrọ naa ba le yanju.
- A kó ní sanwó oṣú ASUU láìjẹ́ pé wọ́n gba IPPIS- Ìjọba Àpapọ̀
- Ìdájọ́ ikú ló bá dé fáwọn méjì tó fipá bá ọmọ ọdún mẹ́rìnlá lò pọ̀
- 'Àwọn ọlọ́pàá tó farapa nínú ìwọ́de EndSARS yóò gba ìgbéga, a ó ṣèrànwó f'ẹ́bí àwọn tó kú'
- Wo bí àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣe n kí fún ìjọba nítorí $1.2bn Naira tó fẹ́ ẹ yá lọ́wọ́ Brazil

Oríṣun àwòrán, @Agborem
Àwọn agbébọn kọlu iléèwé, wọn bọ́ olùkọ́ àti akẹ́kọ̀ọ́ sí ìhòhò
Cameroon students killing: Àwọn agbébọn bíi ogún kọlu iléèwé, wọn bọ́ olùkọ́ àti akẹ́kọ̀ọ́ sí ìhòhò
Àwọn agbébọn kọlu iléèwé, wọn bọ́ olùkọ́ àti akẹ́kọ̀ọ́ sí ìhòhò
Ọkunrin agbebọn bi ogún lo kọlu ileewe girama Kulu memorial comprehensive, to wa ni Gusu orilẹ-ede Cameroon.
Ni ṣe ni awọn agbebọn naa pasẹ fun awọn olukọ ati akẹkọọ, lati bọ ara wọn si ihoho, ki wọn si sa asala fun with ẹ̀mí wọn.
Ikọlu yii waye lẹyin ọjọ kan ti ikọlu kan waye nileewe P S Kumbo. Olukọ mọkanla lo ṣi wa ni ihamọ ajinigbe.
- Banki Nàìjíríà, CBN ṣàlàyé nípa àwọn tó máa rí gbà nínú owó ìrànwọ́ N75b tíjọba gbé kalẹ̀
- Ọkùnrin kan rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́rin he lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìléwọ́ iPhone ní ìpínlẹ̀ Ogun
- ₦50 bílíọ́nù ni a pín fún gbogbo ìpínlẹ̀ ní Naijiria láti kojú àrùn Covid-19- Ìjọba àpapọ̀
- Àwọn ọ̀dọ́ dáná sun ọkọ̀ akérò tó ṣekúpa ọlọ́kadà ní Ibadan
- Oṣú mẹ́fà ni òṣìṣẹ́ ìjọba tó bá bímọ yóò máa lò nílé kó tó wọṣẹ́ padà- Seyi Makinde
Koda, ọjọ mọkanla lẹyin ti wọn pa ọmọde meje ni Kumba, ni iṣẹlẹ naa waye.
Ọjọ kẹrin, oṣu Kọkanla, ni nkan bi aago mẹjọ aabọ owurọ ni ikọlu tuntun yii waye, nigba ti awọn agbebọn wọ inu ileewe naa, ti wọn si pàṣẹ fun olukọ ati akẹkọọ láti bọ aṣọ wọn.
Lẹyin naa ni wọn ko awọn iwe kika àti iwe ẹri jade ni ibi ti wọn ko wọn si, wọn si dana sun wọn.
Bakan naa ni wọn kọlu ọfiisi Ọga Agba ileewe naa, ati ti awọn olukọ.
Awọn alasẹ ileewe naa sọ fún bbc Pidgin pe wọn ko ji ẹni kankan gbé.
"Sugbọn wọn da epo bẹtiro si wọn lara, wọn si tun fi wọn ẹ̀sín."
- A kó ní sanwó oṣú ASUU láìjẹ́ pé wọ́n gba IPPIS- Ìjọba Àpapọ̀
- Diego Maradona ṣiṣẹ́ abẹ lórí ẹ̀jẹ̀ tó dì sí i lọ́pọlọ lẹ́yìn ọjọ́ ìbí ọgọ́ta ọdún
- A ti gbé ìwádìí dìde lórí ìpànìyàn tó wáyé lásìkò ìwọ́de EndSARS- Ilé ẹjọ́ àgbáyé, ICC
- Oyinkan Abayomi, akọni obìnrin tó fi ìfẹ́ pa orúkọ ọkọ kejì dà sí ti ọkọ àárọ̀
Ikọlu naa ni ìkẹta to waye si awọn ileewe laarin ọsẹ meji pere, lasiko ti awọn ajijagbara n gbe igbesẹ lati fi opin si eto ẹkọ ni agbegbe ti wọn ti n sọ èdè Gẹẹsi lorilẹ-ede Cameroon.
Ọdun 2016 ni rogbodiyan bẹrẹ ni agbegbe naa.
Akọsilẹ ajọ isọkan agbaye fihan pe ẹgbẹrun lọna ẹgbẹ̀ta ọmọ ni ko ti i le lọ sileewe.
Nise ni àwọn ajijagbara ti ji ọpọlọpọ olukọ gbé, wọn lu wọn, wọn si tun pa àwọn kan.
- Àlàyé rèé lóríi ìdí tí wọ́n fi ń pe aya ní ìyàwó
- Ọ̀rọ̀ ìjókòó ìgbìmọ̀ ìwádìí #EndSARS náà dé ìpínlẹ̀ Ogun
- Wo iye àwọn tí wọ́n ti gbà sí ikọ̀ SWAT báyìí àti òfin ti wọ́n fún wọn
- Wo bí àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣe n kí fún ìjọba nítorí $1.2bn Naira tó fẹ́ ẹ yá lọ́wọ́ Brazil
- Ẹ wo ẹyẹ ayékòótọ́ tó kó olówó rẹ̀ yọ lọ́wọ́ ikú gbígbóná














