Nigeria Brazil loan: Wo bí àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣe n kí fún ìjọba nítorí $1.2bn Naira tó fẹ́ ẹ yá lọ́wọ́ Brazil

Oríṣun àwòrán, Nig Presidency/ Getty
Ìkéde ìjọba Nàìjíríà láti yá owó lọ́wọ́ Brazil fa awuyewuye
Àwọn ọmọ Naijiria n binu lori ayelujara nitori bi ìjọba ṣe fẹ ẹ ya owo lọwọ ijọba Brazil.
Laipẹ yii ni ijọba orilẹ-ede Naijiria sọ pe oun fẹ ẹ ya owo to le ni biliọnu kan Dọla, $1.2bn, lọwọ orilẹ-ede Brazil, lati fi gbọ bukaata isẹ agbẹ ninu eto isuna ọdun 2021.
Minisita fun eto inawo, eto isuna, ati eto ilu, Zainab Ahmed, lo sọ eyi nibi ipade kan to ṣe pẹlu awọn aṣofin.
O ṣalaye pe awọn ti fi iwe ránṣẹ si awọn aṣofin lati buwọlu owo naa ni yiya.
O ni wọn o lo lara owo naa lati ra ẹgbẹrun lọna ọgọrun eeka ilẹ ni ipinlẹ kọọkan fun ipese oúnjẹ.

Oríṣun àwòrán, @Okwute
Ikede igbesẹ yii ti mu ki awọn ọmọ Naijiria o ma a ṣọ ọrọ kobakungbe si ijọba l'ori owo to fẹ ẹ ya lọwọ Brazil ti 'ipo rẹ ko yatọ si ti Naijiria'.

Oríṣun àwòrán, @YawngBoss
Ẹnikan ti ẹ kọ iwe ránṣẹ si ijoba Brazil "lati ma a ya ijọba Naijiria lowo kankan, nitori pe awa ọmọ orilẹ-ede ko nilo owo yiya.

Oríṣun àwòrán, @Gabriel
A ni nkan alumọọni to pọ... mi o si lero pe a ti san eyi ti a ya lọwọ China".
- Oṣú mẹ́fà ni òṣìṣẹ́ ìjọba tó bá bímọ yóò máa lò nílé kó tó wọṣẹ́ padà- Seyi Makinde
- A ti gbé ìwádìí dìde lórí ìpànìyàn tó wáyé lásìkò ìwọ́de EndSARS- Ilé ẹjọ́ àgbáyé, ICC
- Oyinkan Abayomi, akọni obìnrin tó fi ìfẹ́ pa orúkọ ọkọ kejì dà sí ti ọkọ àárọ̀
- Àlàyé rèé lóríi ìdí tí wọ́n fi ń pe aya ní ìyàwó
- A kó ní sanwó oṣú ASUU láìjẹ́ pé wọ́n gba IPPIS- Ìjọba Àpapọ̀

Oríṣun àwòrán, @Adeyemi
Ẹlomiran sọ pe "ki ẹnikẹni to ba mọ ijọba Brazil bẹ wọn lati ma ya Naijiria lowo, nitori pe wọn n fi àwọn ọmọ ti mi o ti i bi sinu gbẹsẹ".

Oríṣun àwòrán, @Ifeanyi
Folsmith ni ti ẹ sọ pe "ti ao ba ti ri owo da pada fun Brazil, ki wọn o ya a gbẹsẹ le ẹgbẹ agbabọọlu wá".

Oríṣun àwòrán, Ifeanyin
- "Àwọn sójà ní mo káàbò sí ilé ìṣerun àgbáyé tí wọ́n tí ń ṣerun bó ṣe wu wọ́n"
- Ẹ fún wa lówó oṣù wa tàbí kí a gùnlé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ- Àwọn dokita ìpínlẹ̀ Ondo
- Ọkùnrin kan rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́rin he lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìléwọ́ iPhone ní ìpínlẹ̀ Ogun
- A kó ní sanwó oṣú ASUU láìjẹ́ pé wọ́n gba IPPIS- Ìjọba Àpapọ̀
- Àwọn ọ̀dọ́ dáná sun ọkọ̀ akérò tó ṣekúpa ọlọ́kadà ní Ibadan
















