EndSARS Protes Updatet: Aláàfin Ọyọ ní ọ̀dọ́ ìwòyí kò gba gbẹ̀rẹ́, kíjọba yé halẹ̀ mọ́ wọn

Oríṣun àwòrán, Facebook/Alaafin Oba Adeyemi III
Alaafin ilu Oyo, Oba Lamidi Olayiwola Adeyemi ti parọwa si ijọba lati jawọ ninu idukoko mọ awọn ọdọ lẹyin ti wọn ṣe ifẹhọnuhan EndSars ni oṣu to kọja.
Alaafin Oyo sọ eyi lasiko ti awọn gomina ni iwọ-oorun Naijiria, awọn minisita, awọn lọbalọba ni ilẹ Yoruba ṣe ipade pẹlu asoju Muhammadu Buhari. Ọjọgbọn Ibrahim Gambari.
Ipade naa waye lati jiroro lori ọna abayọ si eto aabo to dẹnukọlẹ lorilẹede Naijiria, lasiko ti awọn ọdọ ṣe ifẹhọnuhan tako ifiyajẹni lati ọwọ awọn ọlọpaa.
- Alaafin bi ibeji l‘ẹẹmeji lọsẹ kansoso
- Kí ló ń ṣẹlẹ̀ láàfin Oyo táwọn èèyàn fi ń ki Alaafin ní mẹ́sàn án mẹ́wàá?
- Wò ó bí Alaafin àti aya àkọ́fẹ́ rẹ̀, Olorì Abibat ṣe pàdé ní èwe
- Bí Gómìnà Makinde bá ṣẹ̀ mí, lẹ́tà lásán ló jẹ mí- Aláàfin Ọ̀yọ́
- Àwọn onílù mí ló ń tú àṣírí ìkà èèyàn tó bá wọ ààfin mi - Aláàfin
- Wo ọ̀nà tí àwọn ‘ẹ̀lẹ̀ Daddy’ gbà dé ààfin Ọyọ
Ọba Adeyemi ni ko yẹ ki ijọba ma a dukoko mọ wọn, o yẹ ki ijọba fawọn mọra lati gbọ ẹdun ọkan awọn ọdọ ni.

Oríṣun àwòrán, acebook/Alaafin Oba Adeyemi III
'' Ijọba yẹ ko lo akoko yii lati fi gbọ ohun ti awọn ọdọ nii sọ, ki iru iṣẹlẹ to waye lasiko ifẹhọnuhan EndSars ma ba tun waye.''
''Ijọba gbọdọ woye pe igba yii yatọ si ọgbọn ọdun sẹyin, ti ijọba le e ṣe ohun to wu wọn, ti ko si si ẹni ti yoo beere lọwọ wọn.''
''Awọn ọdọ aye ode oni mọ ẹtọ wọn, wọn si n lo ẹrọ ayelujara lati fi aiṣedede ijọba han si gbangban''
''Nitori naa ni ijọba ṣe gbọdọ lo asiko yii lati fi pẹtu si awọn ọdọ ninu, kii ṣe ki wọn dukoko mọ wọn, tabi gbegile apo owo wọn ni banki, nitori ko bojumu.''
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ṣe lóòtọ́ ni ejò ń pọ owó fún Ginimbi, ọ̀dọ́mọdé olówó kó tó jáde láyé?
- Wo àwọn òṣèré tíátà Yorùbá mẹ́fà tó bẹ̀rẹ̀ eré ṣíṣe láti kékéré
- Mo fi ilé yìí dúpẹ́ lọ́wọ́ ìyá mí fún àtìlẹyìn àti àdúrà rẹ̀ - Emmanuella
- Wo ọ̀pọ̀ àǹfààní tó wà lára ọkọ̀ tó ń lo bátìrì tó sẹ̀sẹ̀ dé Nàíjíríà
- Buhari, a rántí ìjọba rẹ̀ fún ìyà, ìṣẹ́ àti ebi tó peléke - Araàlú faraya
- Bàbá àádọ́rin ọdún fún ọmọ-ọmọ rẹ̀ ọdún mẹ́ẹ̀dógún lóyún, lọ̀rọ̀ bá pèsì jẹ
- Wo iye obìnrin tó bá Ginimbi ọ̀dọ́mọdé olówó kú àti obìnrin to ṣeéṣe kó jogún rẹ̀
- ''Aláàfin kìí ṣe ọkùnrin tí wàá jẹ lásán, tó sì wá sálọ - Aráàlú fèsì fún Olorì Anu
- Wo ọ̀pọ̀ ìgbà tí Ginimbi ọ̀dọ́mọdé olówó ti ṣe àríyá aláṣọ funfun kó tó kú
- Gbogbo ìgbésẹ̀ Aláàfin láti jí mi gbé ló já sí pàbó, n kò le panumọ́ - Olori Anu
Oba Lamidi Olayiwola Adeyemi ni o ṣeni laanu pe awọn kan lo ifẹhọnuhan naa lati da rogbodiyan silẹ, ati ija ẹlẹyamẹya.
Ọba Adeyemi ni awọn dukia ẹya Yoruba nikan ni wọn bajẹ lasiko ifẹhọnuhan to waye ni ipinlẹ Eko, eleyii ti o le jasi ija ẹlẹyamẹya.

Oríṣun àwòrán, others
O ni ki ijọba pada si bi iṣejọba ṣe wa ni saa isejọba tiwantiwa akọkọ lorilẹede Naijiria, ti ẹkun kọọkan n bojuto iṣejọba ara wọn, eleyii to jasi idagbasoke fun ilẹ Yoruba nigba naa.
Oba Lamidi Olayiwola Adeyemi fikun wi pe, ki awọn lọbalọba ri wi pe alaafia jọba ni agbegbe wọn nitori ipa ti oun ko lasiko ifẹhọnuhan naa ni ko jẹ ki o jasi rogbodiyan ni agbegbe oun.
Oba Adeyemi ni oun ko awọn ẹsọ sita lati ma ṣe fun awọn janduku laaye lati ṣekọlu si awọn agọ ọlọpaa lasiko ifẹhọnuhan EndSars naa.
Bakan naa ni Alaafin ilu Oyo ni oun fun awọn to ji awọn nkan gbe lasiko naa ni gbedeke lati da wọn pada, eleyii ti o ni wọn tẹle to si jẹ ki alaafia jọba ni ipinlẹ Oyo.
Ọ̀rọ̀ ìjókòó ìgbìmọ̀ ìwádìí #EndSARS náà dé ìpínlẹ̀ Ogun
Ijoko akọkọ igbimọ iwadii lori iwa ifiyajeni eyi ti ijoba ipinlẹ Ogun gbe kalẹ yoo bẹrẹ lọjọ karun un, oṣu Kọkanla tii ṣe ọjọbọ.Igbimọ naa yoo maa gbọ ẹsun t'awọn eeyan ba gbe wa siwaju rẹ ni gbogbo ọjọ Aje, Ọjọru ati Ọjọbọ ni ile ẹjọ majisireti to wa ni Isabo Abeokuta.

Oríṣun àwòrán, @OGSG
- Banki Nàìjíríà, CBN ṣàlàyé nípa àwọn tó máa rí gbà nínú owó ìrànwọ́ N75b tíjọba gbé kalẹ̀
- Wo àfipábánilòpọ̀ ẹni ọdún 51 tí ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti tú làṣirí ní gbangba
- "Àwọn sójà ní mo káàbò sí ilé ìṣerun àgbáyé tí wọ́n tí ń ṣerun bó ṣe wu wọ́n"
- Àlàyé rèé lóríi ìdí tí wọ́n fi ń pe aya ní ìyàwó
- Ẹ fún wa lówó oṣù wa tàbí kí a gùnlé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ- Àwọn dokita ìpínlẹ̀ Ondo
Atejade kan ti akọwe igbimọ naa Arabinrin Oluwatosin Ogundele fi sita ni igbẹjọ yi ko ni fi igba kan bọkan ninu ti yoo si mọlẹ kedere fara ilu.
Kaakiri awọn ipinlẹ Naijiria ni irufẹ igbẹjọ yi ti n waye ni idahun si ipe arailu si iwa aitọ t'awọn agbofinro paapa ikọ SARS n hu si ara ilu.
- Ọkùnrin kan rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́rin he lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìléwọ́ iPhone ní ìpínlẹ̀ Ogun
- A ti gbé ìwádìí dìde lórí ìpànìyàn tó wáyé lásìkò ìwọ́de EndSARS- Ilé ẹjọ́ àgbáyé, ICC
- Àwọn ọ̀dọ́ dáná sun ọkọ̀ akérò tó ṣekúpa ọlọ́kadà ní Ibadan
- Oṣú mẹ́fà ni òṣìṣẹ́ ìjọba tó bá bímọ yóò máa lò nílé kó tó wọṣẹ́ padà- Seyi Makinde
- A kó ní sanwó oṣú ASUU láìjẹ́ pé wọ́n gba IPPIS- Ìjọba Àpapọ̀
















