Ilé ẹjọ́ tó ń gbọ́ ẹ̀sùn ìwà ọ̀daràn l'àgbáyé, ICC bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ìpànìyàn tó wáyé lásìkò ìwọ́de EndSARS

Ile ẹjọ agbaye to n gbọ ẹsun iwa ọdaran, ICC, ti sọ fun BBC pe oun ti gbe iwadii dide lori ohun to ṣẹlẹ lasiko iwọde #EndSARS ni Naijiria.
Ninu atẹjade kan lati ọọfisi agbẹjọro rẹ, ile ẹjọ naa ni oun ti gba awọn iroyin kan nipa awọn iṣẹlẹ ifẹmiṣofo to waye nibi iwọde ọhun.
Wọn ni ayẹwo awọn yoo sọ boya awọn ṣe ẹjọ ọhun bii ẹjọ titẹ oju ẹtọ ara ilu mọlẹ, tabi iṣekupa ọpọ ero.
- A kó ní sanwó oṣú ASUU láìjẹ́ pé wọ́n gba IPPIS- Ìjọba Àpapọ̀
- Oṣú mẹ́fà ni òṣìṣẹ́ ìjọba tó bá bímọ yóò máa lò nílé kó tó wọṣẹ́ padà- Seyi Makinde
- DPO ọlọ́pàá ju télọ̀ sátìmọ́lé, gbé e lọ sílé ẹjọ́ n'Ibadan torí ''ó ba aṣọ rẹ̀ jẹ́''
- ₦50 bílíọ́nù ni a pín fún gbogbo ìpínlẹ̀ ní Naijiria láti kojú àrùn Covid-19- Ìjọba àpapọ̀
Fun nnkan bi ọsẹ meji ni awọn oluwọde fi fọ si igboro kaakiri Naijiria lati bere fun opin si ẹka ileeṣẹ ọlọpaa to n ri si iwa idigunjale, SARS, ki ijọba pana iwọde ọdhun.
Gẹgẹ bi ọrọ ti Aarẹ Muhammadu Buhari sọ, ara ilu mọkanlelaadọta, ọlọpaa mọkanla ati ọmọ ologun meje ni ẹmi wọn sọnu nitori ifẹhonuhan naa.

- Ọkùnrin kan rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́rin he lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìléwọ́ iPhone ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Ẹ fún wa lówó oṣù wa tàbí kí a gùnlé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ- Àwọn dokita ìpínlẹ̀ Ondo
- Wo àfipábánilòpọ̀ ẹni ọdún 51 tí ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti tú làṣirí ní gbangba
- Ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Oyo jáwée lọ sinmi nílé fún alága ìgbìmọ̀ mẹ́tàlá káàkiri ìjọba ìpínlẹ̀
Ajọ ajafẹtọ ọmọniyan, Amnesty International, sọ pe awọn ọmọ ologun Naijiria ṣina ibọn bolẹ fun awọn oluwọde ọhun lẹnu iloro Lekki Toll Gate, ti ọpọ ku, nigba ti awọn miran si farapa.
Bo tilẹ jẹ pe awọn oṣojumi koro sọ pe awọn ọmọ ileeṣẹ ologun Naijiria lo pa awọn eeyan naa, ṣugbọn ileeṣẹ ọlọpaa ati ileeṣẹ ologun ti ni awọn ko mọwọ mẹsẹ ninu iṣẹlẹ ọhun.
ICC ti wa ni abajade iwadii oun yoo di mimọ fun gbogbo agbaye lati mọ ooto ọrọ naa.
















