Coronavirus cases in Ngeria today: ₦50 bílíọ́nù ni a fún ìpínlẹ̀ kààkan ní Naijiria láti kojú àrùn Covid-19 - Ìjọba àpapọ̀

Oríṣun àwòrán, @NCDCgov
Igbimọ amuṣẹya lori ọrọ Covid-19 ti ijọba apapọ gbe kalẹ, PTF, ti sọ pe awọn ipinlẹ kaakiri Naijiria ti gba owo ti iye rẹ ko din ni aadọta biliọnu naira lati koju arun naa.
Adari PTF, dokita Sani Aliyu lo kede bẹẹ nibi ipade awọn akọroyin to waye niluu Abuja.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, iye to kere ju ti ipinlẹ kọkan gba lati koju Covid-19 ko din ni biliọnu kan naira.
- Ẹ fún wa lówó oṣù wa tàbí kí a gùnlé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ- Àwọn dokita ìpínlẹ̀ Ondo
- Ọkùnrin kan rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́rin he lẹ́yìn tó jí ẹ̀rọ ìléwọ́ iPhone ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Wo àfipábánilòpọ̀ ẹni ọdún 51 tí ìjọba ìpínlẹ̀ Ekiti tú làṣirí ní gbangba
- Ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Oyo jáwée lọ sinmi nílé fún alága ìgbìmọ̀ mẹ́tàlá káàkiri ìjọba ìpínlẹ̀
O ni awọn ipinlẹ ni agbara lati koju arun naa nitori iye owo ti wọn ti gba lọwọ ijọba apapọ to ṣe nnkan.
Aliyu ni "a ti fun awọn ipinlẹ ni owo gọbọi lati koju Covid-19, ko sì sí ipinlẹ to gba owo ti iye rẹ kere ju biliọnu kan naira lọ."

Oríṣun àwòrán, @NCDCgov
O tẹsiweaju pe "Bi a ṣe n sọrọ lọwọ yii, 50 biliọnu ni a ti fi ranṣẹ si gbogbo ipinlẹ ni Naijiria ati Abuja, nitori naa, a ní gbogbo nnkan ti yoo gba lati le Coronavirus jina si awujọ wa."
Dokita ọhun ni afujusun ijọba apapọ ni lati ri daju pe arun Covid-19 di ohun igbagbe ni Naijiria.
Lẹyin naa lo ni ijọba apapọ yoo tẹsiwaju lati maa ṣiṣẹ papọ pẹlu awọn ijọba ipinlẹ lati lo owo naa gẹgẹ bo ṣe tọ ati bo ṣe yẹ.
Aliyu pari ọrọ rẹ pẹlu arọwa pe ki awọn ijọba ipinlẹ má na owo naa si awọn nnkan miran bi ko ṣe lati koju Coronavirus nikan.
- 'Ìdí tí kámẹ́rà táa rí ní Lekki Tollgate kò fi ká gbogbo ìṣẹ̀lẹ̀ tó wáyé rè é'
- "Àwọn sójà ní mo káàbò sí ilé ìṣerun àgbáyé tí wọ́n tí ń ṣerun bó ṣe wu wọ́n"
- Ìjọba ti buwọ́lu lílo hijab láwọn iléèwé ní ìpínlẹ̀ Osun
- A ó ṣèrànwọ́ fáwọn ẹbí ọlọ́pàá tó bá rògbòdìyàn EndSARS lọ láti inú N500m tí a yà sọ́tọ̀- Makinde

















