Kabex End SARS: Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó làmìlaaka tó wáyé nínú oṣù Kẹ́wàá ọdún 2020

Oríṣun àwòrán, @thecableng
Oṣu kẹwaa ọdun 2020 jẹ oṣu kan ti ọpọlọpọ awọn ọmọ Naijiria ko lee gbagbe ninu itan nitori awọn iṣẹlẹ to waye ninu oṣu ọhun.
Lara awọn iṣẹlẹ manigbagbe naa ree:
Iwọde #EndSARS
Iwọde EndSARS bẹrẹ lẹyin ti fidio kan fa ori ayelujara ya lọjọ kẹta, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020, eyii to ṣafihan bi awọn ọlọpaa SARS ṣe yinbọn fun ọkunri na niwaju ile itura Wetland, to wa ni Ugheli, ni ipinlẹ Delta.
- Buhari, dẹ́kun à ti máa lọ sókè òkun fún ìtọ́jú, tún ilé ìwòsàn Aso Rock ṣe- Sẹ́nátọ̀
- Mo ṣetán láti dojú ìjà kọ ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ bá ọ̀rọ̀ ajé Eko jẹ́- Sanwo Olu
- Bí àwọn kan tí ń ní àtimọ̀lé tí wọ́n sọ olorin Nazir sí ní Kano ni ọwọ́ kan òṣèlù ní àwọn mii ní...
- Sanwo-Olu buwọ́lu ìgbésẹ̀ ìjọba láti tún Eko ṣe lẹ́yìn rògbòdìyàn EndSARS
Iṣelẹ naa lo ta epo si ifẹhonuhan EndSARS lori ikanni Twitter.

Oríṣun àwòrán, @thecableng
Ṣugbọn nigba ti iyẹn ṣi n lọwọ, ni iroyin kan tun jade pe awọn oṣiṣẹ SARS tun ti pa olorin takasufe kan to jẹ ọmọ ogun ọdun, ti orukẹ rẹ n jẹ Daniel Chibuike.
Lẹyin naa ni awọn eeyan bẹrẹ iwọde kaakiri awọn ilu nla ni Naijiria ati loke okun, ti wọn si n ke gbajare si ijọba apapọ pe ko fi opin ẹka ileeṣẹ ọlọpaa SARS naa.
Igba to di ọjọ kẹjọ, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020 ni iwọde ita gbangba bẹrẹ ni pẹrẹwu, ti ọpọ awọn gbajumọ ni Naijiria ati kaakiri agbaye si n sọ pe wọn fi ọwọ si iwọde ọhun.
Ifẹmiṣofo ni Lekki Toll Gate
Ni nnkan bi aago mẹfa abọ ogunjọ, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020, ni awọn ẹṣọ alabo ṣina ibọn bolẹ fun awọn oluwọde to kọ lati fi iloro naa silẹ lẹyin ti ijọba ipinlẹ Eko ti kede ofin konile-o-gble oni wakati mẹrinlelogun.

Oríṣun àwòrán, @jharmo
Olorin takasufe kan, Dj Switch ka iṣẹlẹ naa silẹ loju opo Instagram rẹ, to si sọ pe awọn ọlọpaa atawọn ọmọ ogun lo ṣiṣẹ ibi naa, ṣugbọn ileeṣẹ ologun ti ni oun ko mọwọ mẹsẹ ninu iṣẹlẹ ọhun.
Jiji ounjẹ iranwọ Covid-19 ko
Lẹyin ti iwọde EndSARS gbọna mii yọ ni awọn janduku ja iwọde naa gba, ti wọn si bẹrẹ sii kọlu awọn ile ti ijọba ko ounjẹ iranwọ Covid-19 pamọ si.
Wọn ni o yẹ ki ijọba ti pin awọn ounjẹ naa, ṣugbọn wọn ko pa lati lu ni gbanjo.

Oríṣun àwòrán, @CDDWestAfrica
Awọn miran tun ṣakọlu si ọpọ agọ ọlọpaa ni ipinlẹ Eko, alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko tilẹ sọ fun BBC pe ko din ni agọ ọlọpaa marundinlogun ti awọn janduku naa dana sun.
Ikọlu gomina ipinlẹ Osun
Ọjọ kọkandinlogun oṣu Kẹwaa yii kan naa ni awọn janduku kan ṣakọlu si gomina ipinlẹ Osun, Gboyega Oyetola, nibi iwọde EndSARS ni ilu Osogbo.
Awọn janduku ọhun sọ oko, kondo atawọn ohun ija miran si gomina ọhun, ti awọn eeyan si farapa.
Awọn ẹlẹwọn salọ ni Edo
Igba ti iwọde EndSARS n lọwọ ni awọn janduku kọlu ọgba ẹwọn to wa ni opopona Sapele, ti wọn si tu awọn ẹlẹwọn silẹ.
Nnkan bi ẹgbẹrun meji ẹlẹwọn ni awọn janduku naa fun ni ominira, eyii to mu ki gomina Godwin Obaaseki kede igbele oni wakati mẹrinlelogun.
Igbohunsafẹfẹ Aarẹ Muhammadu Buhari
Lẹyin ti iwọde EndSARS ti bẹrẹ lọpọ eeyan kaakiri Naijiria ti n reti ki Aarẹ Muhammadu Buhari sọrọ soke ṣugbọn ko wi nnkan.
Ẹwẹ, lẹyin ti awọn ṣọja yinbọ fun awọn oluwọde ni iloro Lekki, ti gbogbo ọrọ si dojuru ni Aarẹ to sọrọ soke.
Ṣugbọn o ṣeni laanu pe igbohunsafẹfẹ naa ko tẹ awọn ọmọ Naijiria lọrun nitori wọn ni ọkọ Aisha ko mẹnuba ohun ti wọn reti ko sọ.
Bi awọn kan ṣe n sọ pe ifakoko ṣofo lasan ni igbohunsafẹfẹ naa lawọn miran n sọ pe ki ṣe Aarẹ lo ṣe igbohunsafẹfẹ ọhun.
















