Ooni Ile Ife marriage: Mọ̀ síi nípa àwọn Obìnrin tó wà láyé Ooni Ogunwusi Adeyeye ṣáájú Olòrì Naomi SilekunOla

Oríṣun àwòrán, Others
Lati ọjọ kẹtalelogun, oṣu kejila ọdun yii ti Olori Naomi Silekunola aya Oba Adeyeye Ogunwusi to jẹ Ooni ti IleIfe ti kede lori ayelujara pe o toge ni oriṣiriṣi iroyin ti n jade.Olòrì Silekunola Naomi Ogunwusi: Mo ti sún síwájú, mo gbìyànjú pé kí ìgbèyàwó yìí ṣiṣẹ́ ṣùgbọ́n....
Eyi lo jẹ ki BBC Yoruba lọ ṣe iwadii awọn irpyin to n kede ọpọlọpọ obinrin fun Ooni naa pe wọn jẹ aya rẹ yatọ si Olori Naomi.
Opọ ninu awọn iroyin naa jẹ ofege nitori ko si akọsilẹ to ṣe e fihan pe nitootọ ni kabiesi Ogunwusi fẹ awọn obinrin mẹwaa naa ti ọpọ n sọ nipa wọn lori ayelujara.
Obinrin mẹrin wọnyii nikan ni akosile ojutaye wa nipa wọn ati akoko ti wọn fi wa pẹlu Ojaja keji.
- Kà nípa ìbẹ̀rẹ̀ ìyàwó Ooni Ife, Olórí Silekunola Moronke Náómì, Wòlíì tó di Ayaba Ile Ife
- Ta ni Ashley Folasade Adegoke ti ayé ń pariwo pé òun ni Olorì tó máa rọ́pò Naomi Silekunola?
- Ooni ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ẹ̀bùn tuntun ta Olorì Naomi lọ́rẹ tán ní, ìfẹ́ wọn dúró, kò sí ìpínyà- Aàfin Oòdúà
- Ẹ fura àwọn agbésùmọ̀mi láti Mali fẹ́ wọ ìlú Abuja
- Ifasooto gbòmìnira lẹ́yìn oṣù mẹ́fà látìmọ́lé DSS lórí ẹ̀sùn pé ó ń ṣ'òògùn fún Sunday Igboho
Obinrin akọkọ ti igba oju mọ pẹlu Oba Adeyeye Ogunwusi ni arabinrin Omolara Olatubosun.
Odọmọde ti ko tii pe ẹni ogun ọdun ni awọn mejeeji lasiko ti wọn jọ n rin papọ ki o to di oyun ti wọn fi bi Ọmọbabinrin Adeola Ogunwusi ni o din diẹ ni ọgbọn ọdun sẹyin.
Adebukola Bombata ni obinrin imii to jade ninu aye Oba Ogunwusi ṣaaju ki o to jẹ Oba Ile Ife.
Lọdun 2008 ni wọn ṣe igbeyawo ni won jọ gbe papọ ki onikaluku to pin gaari.

Oríṣun àwòrán, @Others
Bi awọn kan ṣe sọ pe Adebukola fi Ooni Ogunwusi silẹ lọdun 2015 nitori pe ipo Oba naa ko wu u ni àwọn mii ni pe nkan miran lo jẹ ki wọn fi ara wọn silẹ.
- Èyí ni ìdí tí Bàbá Kérésì fi máa n wọ aṣọ pupa àti funfun nígbà gbogbo
- Wo ọ̀nà mẹ́wàá tí o fi lè dábò bo ara ré lásòkò ọyẹ́ yìí
- Àjọ aṣọ́bodè gbẹ́sẹ̀ lé òògùn ìbálòpọ̀ ẹ́gbẹ̀lẹ́gbẹ̀ mílíọ̀nù ní ìpínlẹ̀ Katsina
- Ọ̀fẹ́ ni ọkọ̀ ojú irin akérò yóò máa kó àwọn arìnrìnàjò lásìkò pọ̀pọ̀ṣìnṣin ọdún yìí - Ìjọba àpapọ̀
- Mọ̀ síi nípa Olorì Abibat Nihinlola Adeyemi tó ti lo ọdún 60 gẹ́gẹ́ bíi olorì láàfin Alaafin Oyo
Lọdun 2015 lẹyin ti Ooni gori aleefa itẹ awọn baba nla rẹ ni o gbiyanju iyawo miran.
Ooni ko duro nile Yoruba rara lati lọ mu arẹwa to wu Kabiesi.
Benin ni ipinlẹ Edo to jẹ ọmọ iya Oodua ni Oba Ogunwusi ti lọ gbe Olori Zainab Otiti Obanor Wuraola.
Igbeyawo naa si wa sopin lọdun 2017.
Lọdun 2018 ni Oba Adeyeye Ogunwusi gbe Ajihinrere obinrin Naomi Silekunola lati ipinlẹ Ondo ni iyawo.
Oba Oke fi omokunrin lantilanti, Tadenikawo Ogunwusi ta wọn lọrẹ lọdun to kọja.
Igbeyawo yii ni Olori Naomi si wa kede lori ayelujara bayii pe oun ti sun siwaju nitori pe oun fẹ gbajumọ ṣiṣe iya ọmọ rẹ Tadenikawo.
Ikede yii ni Moses Olafare agbenuso fun Ile Oodua ni Ile Ife sọ fun BBC Yoruba pe wọn ko mọ nkankan nipa rẹ nitori pe Ooni ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ẹ̀bùn tuntun ta Olorì Naomi lọ́rẹ tán ní, ìfẹ́ wọn dúró, kò sí ìpínyà- Aàfin Oòdúà


















