Nigeria security threath from immigration: Ẹ fura àwọn agbésùmọ̀mi láti Mali fẹ́ wọ ìlú Abuja

Oríṣun àwòrán, @Others
Awọn agbésùmọ̀mi lati Mali ń gbèrò láti wọ àwọn ààlà Nàìjíríà láti kọlu olú-ìlú Abuja, awọn òṣìṣẹ́ tó ń rí sí ìwọlé àti ìjáde lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe titaniji fún àwọn òṣìṣẹ́ wọn.
Ile-iṣẹ tó ń rí sí ìwọlé àti ìjáde lorilẹ-ede Naijiria ti fi awọn oṣiṣẹ ijọba rẹ si oriṣiriṣi awọn ibudo aala kaakiri orilẹ-ede yìí itaniji láti dènà ikọlu àwọn agbésùmọ̀mi sí oluilu orilẹede Nàìjíríà Abuja.
Lẹta naa ti wọn kọ ranṣẹ ni ọjọ ketalelogun, Oṣu kejila, ọdun 2021, pẹlu akole rẹ,
‘Awọn agbésùmọ̀mi fẹ ṣe ikọlu si Abuja’ ti Alakoso ikọ tó ń mójú to aala orilẹ, Edirin Okoto, sì fowo si ni orukọ Adele ọga àgbà ajọ alábòójútó ìjáde àti ìwọlé ni Nàìjíríà Idris Jere.
- Ìjọba Nàìjíríà kéde ìlànà tuntun lórí COVID-19, Ó mú àdínkù bá ìye èèyàn tó lè wọ ṣọ́ọ̀ṣì, mọ́sáláṣí
- Mọ̀ síi nípa Olorì Abibat Nihinlola Adeyemi tó ti lo ọdún 60 gẹ́gẹ́ bíi olorì láàfin Alaafin Oyo
- Ta ni Ashley Folasade Adegoke ti ayé ń pariwo pé òun ni Olorì tó máa rọ́pò Naomi Silekunola?
- Ẹ̀yin olùgbé ìlú Eko, ẹ má bẹ̀rù, bílíọ̀nù mẹ́ta ni a ná lórí ọlọ́pàá lọ́dún 2021- Sanwo-Olu
- Ooni ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ẹ̀bùn tuntun ta Olorì Naomi lọ́rẹ tán ní, ìfẹ́ wọn dúró, kò sí ìpínyà- Aàfin Oòdúà
Iwe naa ti wọn kọ ranṣẹ ni wọ́n fi ranṣẹ si gbogbo awọn alaṣẹ aladani ati awọn ọlọpa aala ni gbogbo orilẹ-ede Nàìjíríà.
Lara awon ti won wa ni Seme, Idi Iroko, Jibia, aala Illela pelu awon osise mìíràn to wa ni papakọ ofurufu Murtala Mohammad, papakọ ofurufu Nnamdi Azikwe, papakọ ofurufu Mallam Aminu Kano, láàrin awon miran.
O ka, báyìí pé. “Láti ọfiisi ti Ag CGI lẹyin ifiweranṣẹ to ni pajawiri lati ọdọ Alakoso (OSGF).
Àwọn kan ń gbiyanju lati ṣe ikọlu si Ilu Abuja tí ṣe Olu-ilu Naijiria, laarin ọjọ ti kẹtala ati ọjọ kọkanlelogbọn, Oṣu kejila, ọdun 2021.
Ikọlu tí wọ́n ń pinnu naa ni wọn sọ pe o jẹ eyi ti oludari DRAHMANE ń pinnu. OULD ALI, aka Mohammed Ould Sidat, ọmọ orilẹ-ede Algeria pẹ̀lú l iranlọwọ. Zahid Aminon, ọmọ orilẹ-ede Niger kan.
“Ijabọ naa tọka sì pe awọn mejeeji naa n bọ wa si Nigeria lati Mali tí wọ́n yoo si gba Gan ati Niger Republic kọja pẹlu tọkọ Toyota Hilux funfun kan tó ní àkọsílẹ̀ idanimọ AG157EKY.
Wọn fi kún wipe awọn meji wọnyi ni awọn ẹlẹgbẹ mẹ́rin mìíràn ni Naijiria ti wọn ti wa nilẹ lati ra wọn lọwọ.
“O tun ni pe Ali gba iwe irinna Algerian pẹlu orukọ Najim Ould Ibrahim.

















