Ooni of Ife: Oba Adeyeye Ogunwusi ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ẹ̀bùn tuntun ta Olorì lọ́rẹ tán ní, ìfẹ́ wọn dúró, kò sí ìpínyà- Aàfin Oòdúà

Oríṣun àwòrán, Ooni Adeyeye Enitan Babatunde Ogunwusi - Ojaja II
Kii ṣe iroyin tuntun mọ pe Olori Ọọni ile ifẹ kọwe sori ayelujara lọjọbọ nipa igbesẹ rẹ lati sun siwaju lori igbeyawo oun ati Ọọni Ogunwusi.Olòrì Silekunola Naomi Ogunwusi: Mo ti sún síwájú, mo gbìyànjú pé kí ìgbèyàwó yìí ṣiṣẹ́ ṣùgbọ́n....
Amọṣa aafin Ọọni nilu Ile Ifẹ tii ṣe ile Oodua ti sọ pe kosi ohun to jọọ rara.
Kabiyesi Ọọni lọwọ ti a n sọrọ ṣi n sọ pe oun ṣi ni ọkọ Olori Ṣilẹkunọla, ko si si oun kan to n jẹ ipinya laarin awọn mejeeji.
- Kí ló dé tí Ooni Ile Ife fẹ́ gbẹ̀mí ara rẹ̀?
- Ta ni Ashley Folasade Adegoke ti ayé ń pariwo pé òun ni Olorì tó máa rọ́pò Naomi Silekunola?
- Ẹ̀yin olùgbé ìlú Eko, ẹ má bẹ̀rù, bílíọ̀nù mẹ́ta ni a ná lórí ọlọ́pàá lọ́dún 2021- Sanwo-Olu
- Ìjọba Osun jáwe lọ rọọ́kún nílé fún olùkọ̀ nítorí pé ó sọ̀rọ̀ tako ìjọba lórí Facebook
Ninu ọrọ ti agbẹnusọ fun Kabiyesi Ọọni Adeyẹye Ogunwusi, Oloye Moses Ọlafare ba BBC News Yoruba sọ, o ni bi gbogbo eeyan ṣe ri atẹjade naa lori ayelujara ni Kabiyesi ati aafin ile Oodua naa ṣe rii.
Ati pe titi di bi a ṣe n sọrọ yii igbesẹ naa ṣajeji si aafin Ọọni ati itẹ Ooni funrarẹ.

Oríṣun àwòrán, Ooni Adeyeye Enitan Babatunde Ogunwusi - Ojaja II
Oloye Ọlafare ni eyi ko sọ pe ko lee si awọn ipenija kọọkan laarin wọn o, nitori ko si igbeyawo ti kii ni ipenija tirẹ.
"Ipinya ninu igbeyawo kii ṣe ohun ti eeyan n gbe jade lori ayelujara. Ko si nnkan to n jẹ ipinya laarin wọn"
Agbẹnusọ fun Ọọni Ogunwusi ṣalaye pe titi alẹ ọjọru to ṣaaju Ọjọbọ ti atẹjade naa jade loju opo ayelujara Olori Ṣilẹkunọla, kabiyesi ati olori rẹ ṣi wa papọ ti wọn jọ ṣere.
Koda, Olafare ni ọjọru ni kabiyesi fi ẹbun nla yunyun kan taa lọrẹ.
Aafin Oodua ni bi a ba n sọrọ ikọsilẹ ninu igbeyawo, ati ọkọ, ati iyawo lo maa jumọ fi ọwọ si pe awọn fẹ pinya Ko si ohun, kii ṣe lilọ polongo lori ayelujara ni.
















