Christmas Eve message: Ìjọba àpapọ̀ ní ọ̀fẹ́ ni ọkọ̀ ojú irin akérò yóò máa kó àwọn arìnrìnàjò lásìkò pọ̀pọ̀ṣìnṣin ọdún

Oríṣun àwòrán, @OvieAli
Ijọba apapọ ti kede pe ọfẹ ni ọkọ oju irin akero yoo ba de fun gbogbo araalu lasiko pọpọṣinṣin ọdun Keresimesi.
Ikede yii lo jade lati ọọfisi ileeṣẹ ijọba apapọ to n ri si ọrọ ọkọ oju irin akero ni Naijiria, NRC.
Wọn ni awọn gbe igbesẹ naa ki awọn araalu le ri aye lati rinriajo lọ ba awọn ẹbi wọn ṣe ọdun.
- Ẹ fura àwọn agbésùmọ̀mi láti Mali fẹ́ wọ ìlú Abuja
- Ìjọba Nàìjíríà kéde ìlànà tuntun lórí COVID-19, Ó mú àdínkù bá ìye èèyàn tó lè wọ ṣọ́ọ̀ṣì, mọ́sáláṣí
- Ooni ṣẹ̀ṣẹ̀ fi ẹ̀bùn tuntun ta Olorì Naomi lọ́rẹ tán ní, ìfẹ́ wọn dúró, kò sí ìpínyà- Aàfin Oòdúà
- Mọ̀ síi nípa Olorì Abibat Nihinlola Adeyemi tó ti lo ọdún 60 gẹ́gẹ́ bíi olorì láàfin Alaafin Oyo
- Ta ni Ashley Folasade Adegoke ti ayé ń pariwo pé òun ni Olorì tó máa rọ́pò Naomi Silekunola?
- Ẹ̀yin olùgbé ìlú Eko, ẹ má bẹ̀rù, bílíọ̀nù mẹ́ta ni a ná lórí ọlọ́pàá lọ́dún 2021- Sanwo-Olu
- Olòrì Silekunola Naomi Ogunwusi: Mo ti sún síwájú, mo gbìyànjú pé kí ìgbèyàwó yìí ṣiṣẹ́ ṣùgbọ́n....
- Ìjọba Osun jáwe lọ rọọ́kún nílé fún olùkọ̀ nítorí pé ó sọ̀rọ̀ tako ìjọba lórí Facebook
- Mọ̀ síi nípa Bola Ige tó jẹ́ mínístà ètò ìdájọ́ ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣì ń wá ìdájọ́ òdòdo lórí ikú rẹ̀
Agbẹnusọ ileeṣẹ naa, Yakub Mahmood ni awọn ọkọ oju irin akero ti ọrọ naa kan ni eyii to n ko ero lati Abuja si Kaduna, Eko si Ibadan, Warri si Itakpe, Kano si Eko, Minna si Kaduna ati Abba si Port Harcourt.
Awọn eeyan le bẹrẹ si n wọ ọkọ oju irin naa lọfẹ lati ọjọ Ẹti, ọjọ kẹrinlelogun, oṣu Kejila, ọdun 2021, titi di ọjọ kẹrin, oṣu Kinni, ọdun 2022.
Amọ NRC sọ pe gbogbo awọn arinrinajo ti ọrọ naa kan gbọdọ gba tikẹẹti, bo tilẹ jẹ pe wọn ko ni san owo tikẹẹti naa.
NRC tun sọ pe gbogbo awọn arinrinajo gbọdọ tẹlẹ awọn ilana to rọ mọ Covid-19.
Lẹyin naa ni wọn rọ awọn araalu lati fi akoko ti wọn n wọn ọkọ oju irni ọfẹ naa gbadura fun alaafia ati ilọsiwaju Naijiria.














