Wo ọ̀nà mẹ́wàá tí o fi lè dábò bo ara ré lásìkò ọyẹ́ yìí

Oríṣun àwòrán, Olorunfemi Vincent
Akoko ọyẹ jẹ akoko kan ti awọn ọmọ Naijiria maa n reti lati oṣu Kọkanla titi di aarin oṣu Kẹta ọdun keji.
Akoko naa jẹ asiko ti atẹgun maa n fẹ lati iha Ariwa ila oorun, tabi lati ila oorun si iwọ oorun Sahara.
Oniruru orilẹ-ede lo ni akoko ti oju ọjọ wọn maa n yipada, fun apẹrẹ, lawọn agbegbe kan Yuroopu, yinyin maa n jabọ lati oju ofurufu.
Ni Naijiria ẹwẹ, a ni igba ojo, a si tun ni igba ẹrun.
- Ta ni Ashley Folasade Adegoke ti ayé ń pariwo pé òun ni Olorì tó máa rọ́pò Naomi Silekunola?
- Ènìyàn Mẹ́ta kú, Mẹrin Farapa bí ọkọ̀ ńlá ṣe rọ́lu àwọn ènìyàn ni Mokola ní Ibadan
- Mọ̀ síi nípa Olorì Abibat Nihinlola Adeyemi tó ti lo ọdún 60 gẹ́gẹ́ bíi olorì láàfin Alaafin Oyo
- Ìjọba Nàìjíríà kéde ìlànà tuntun lórí COVID-19, Ó mú àdínkù bá ìye èèyàn tó lè wọ ṣọ́ọ̀ṣì, mọ́sáláṣí
- Ẹ fura àwọn agbésùmọ̀mi láti Mali fẹ́ wọ ìlú Abuja
Igba ojo maa n bẹrẹ lati inu oṣu Kẹrin ọdun si oṣu Kẹwaa, nigba ti akoo ẹrun maa n bẹrẹ inu oṣu Kọkanla si oṣu Kẹta.
Wo awọn ohun ti o le ṣe lati koju akoko ọyẹ yii;
- Maa mu omi ni gbogbo igba
- Maa wọ awọn aṣọ ti yoo daabo bo ara rẹ lọwọ otutu
- O le maa lo oogun "Vitami C" ni gbogbo igba lọna ati maa fun ara rẹ lokun
- Lo awọn ipara ti yoo jẹ ki ara rẹ maa jọlọ
- Ṣora fun ina
- Ṣora fun awọn agbege ti eruku pọ si
- Ṣe irun ti yoo dabo bo ori rẹ
- Maa fi omi fọ oju rẹ loorekoore ki oju rẹ ma ba maa pọn
- Lo ikunra si ete rẹ ki ete naa ma baa gbẹ
- Maa jẹ ọpọ esọ lọna ati ṣe ara rẹ loore












