BBC Yoruba: Àwọn ìròyìn tó tayọ lọ́sẹ̀ yìí

Oríṣun àwòrán, BBC, OTHERS
Lati ọjọ́ aiku ti ọsẹ n bẹrẹ, oniruuru ni awọn iroyin to maa n jade lati akata BBC Yoruba. Bí wọn se pọ to, awọn koko iroyin kan wa to jẹ manigbagbe.

Yinka Ayefele di Bàbá ìbẹta


Oríṣun àwòrán, @Yinkaayefele
Gbajugbaja olorin ni to tun jẹ oludaleeṣẹ rẹdio silẹ, Yinka Ayefẹlẹ ti di baba ibẹta bayii.
BBC Yoruba ba gbajugbaja olorin nni to tun jẹ oludaleeṣẹ redio silẹ, Yinka Ayefẹlẹ sọrọ lati fi aridaju rẹ han pe ni bayi, o ti di baba ibẹta lootọ.
Ṣaaju ni nkan bii oṣu diẹ sẹyin ni iroyin kan tan kalẹ pe o bimọ ti o si ni irọ ni awọn eniyan n pa.
Ṣugbọn ni bayii oun funra rẹ lo tu iroyin ayọ yii fun awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ redio rẹ pe.
Lati mu aridaju wa fun yin la fi ṣe ifọrọwanilẹnuwo yii pẹlu baba ibẹta gan funra rẹ to si ṣalaye gbogbo ọrọ.
Ẹkunrẹrẹ lori iroyin yii wa ni:

Ṣé kí àwọn Fulani Darandaran padà sílé tàbí dúró síbi tí wọ́n wà?


Oríṣun àwòrán, AFP
Ìbẹ̀rẹ̀ ọrọ yii gan ni asiko ti ijọba apapọ ni awọn fẹ da eto RUGA Settlement silẹ eyi ti ọpọlọpọ ti fun ni itumọ tiwọn ti wọn si fẹ loju kaakiri gbogbo ipinlẹ orilẹede Naijiria.
Ileeṣẹ aarẹ orileede Naijiria ni ohun iyalẹnu lo jẹ fawọn bi awọn Gomina ipinlẹ kan ti ṣe n tapa si idasilẹ agọ Fulani, eyi ti wọn pe ni ''Ruga Settlement.''
Bẹẹ naa ni awọn Gomina ipinlẹ kan kilọ fun ijọba pe, ko ma ṣe daba lati da awọn agọ wọnyii silẹ lagbegbe awọn.
Agbẹnusọ fun ileeṣẹ aarẹ, Femi Adesina sọ fun BBC pe, awọn ni akọsilẹ ibi tawọn Gomina kan ti fọwọ si kikọ ọgba fun dida ẹran, lati fi dẹkun wahala to n waye laarin awọn agbẹ ati darandaran.
Ẹkunrẹrẹ lori iroyin yii wa ni:
- Ààrẹ Buhari jámi lórí ètò RUGA ná
- Osinbajo ta kété sí ọ̀rọ̀ 'Ruga Settlement'
- Ẹ̀tàn lásán ni ìkéde ìjọba àpapọ̀ lórí RUGA - Afenifere
- Ìpínlẹ̀ Oyo àti Eko kò nífẹ̀ẹ́ láti gba 'Ruga Settlement' láyè
- Ẹ̀yin tẹ́ẹ tako àgbékalẹ̀ àgọ́ Fulani, ìkórira ló ń yọ yín lẹ́nu - Ìjọba àpapọ̀
- Ẹ má dá NEF lóhùn, kò síbi t'ọ́mọ Nàìjíríà kò lè gbé nílẹ̀ yìí - Buhari

Alhaji Sikiru Ayinla Kollington: Rashidi Yekini ṣì ni mí b'óbìnrin bá sún mọ́ mi


Gbajugbaja olorin Fuji nni, Alhaji Ayinla Kollington ti kede fun araye pe titi aye ni akọrin Waka nni, Alhaja Salawa Abẹni yoo maa jẹ iyawo oun, ti awọn yoo si jọ pẹ fun ara awọn.
Kollington kede eyi lasiko to n dahun ibeere lori eto BBC Yoruba, tun salaye pe obinrin to bi ọmọ fun ni, ti kuro ni ale ẹni, ọmọ mẹta si ni Salawa Abẹni bi fun oun, nitori naa, iyawo oun nii se.
Bakan naa o mẹnu ba a pe lootọ ni ija wa laarin oun ati Alhaji Ayinde Barryster sugbọn bii ti iku kọ tori "bi kii ba ṣe Barry ni iṣẹ aṣọle ni mi o ba maa ṣe".
Ọrọ pọ ninu iwe kọbọ ti gbajugbaja olorin yii tu sita fun BBC Yoruba.
Ẹkunrẹrẹ lori iroyin yii wa ni:
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post, 1

Ikọ̀ Super Eagles padà wálé lẹ́yìn tí wọ́n tún gba Bronze lẹ́ẹ̀kẹjọ


Diẹ to ninu nnkan oni nnkan, eyi lo difa fun ẹgbẹ agbabọọlu Naijiria, Super Eagles ti wọn ipo kẹta tawọn nnkan n pe ni golden bronze ninu idije AFCON 2019.
Lẹyin iṣẹju mẹta pere ti wọn bẹrẹ ere bọọlu ọhun ni ẹlẹsẹ ayo, Odion Ighalo gba bọọlu sawọn eyi to fun Naijiria lanfani lati siwaju ninu ifẹsẹwọnsẹ to kangun si aṣekagba.
Bi a ba ka a ni meni meji, igba ikẹjọ ree ti ik Super Eagles yoo gba ami ẹyẹ baba kan naa, Bronze.
Ni bayii, ikọ naa ti pada wale pẹlu akọnimọọgba wọn, Gernort Rohr.
Ẹkunrẹrẹ lori iroyin yii wa ni:
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post, 2

Face App: Ẹ wo báwọn òṣèré tíátà kan yóò ṣe rí lọ́jọ́ ogbó


Oríṣun àwòrán, LATEEF ADEDIMEJI
Pitimu ni awọn oju opo ayelujara Facebook, Instagram ati Twitter kun fun App ori ayelujara kan ti wọn n pe ni Face App lọsẹ yii.
Ọpọlọpọ awuyewuye lo ti n lọ lori lilo ẹrọ to n pa ọjọ ori ẹni da FaceApp, ti o le mu ki aworan eniyan kere sii ni ọjọ ori, abi ki o dabi arugbo.
Gbogbo oju opo ayelujara lo ti kun bayii fun fọto awọn oṣere tiata, ti wọn parada di arugbo bẹ si ni awọn ọmọ Naijiria naa ti dara pọ mọ eyi.
Ẹkunrẹrẹ lori iroyin yii wa ni:

Yánpọn yánrin lórí ikú ọmọ Alága ẹgbẹ́ Afenifere, Fasoranti


Oríṣun àwòrán, OTHER
Pẹlu iroyin ojiji ti ọpọlọpọ n sọ nipa iku ọmọ alaga ẹgbẹ Afenifere ti ilẹ Yoruba, ọpọ gbọ yii sọ yii lo ti n jẹ jade lori boya Fulani daran daran tabi awọn agbebọn lo pa Funkẹ Ọlakunrin.
Lasiko to n fi idi isẹlẹ naa mulẹ fun BBC Yoruba, agbẹnusọ fun ẹgbẹ Afẹnifẹre, Yinka Odumakin salaye pe lootọ ni isẹlẹ naa waye, asiko ti Ọlakunrin n bọ lati ilu Akurẹ si lo se alabapade iku ojiji naa.
Baba oloogbe naa ni alaga ẹgbẹ Afẹnifẹre, alagba Reuben Fasoranti.
Ẹkunrẹrẹ lori iroyin yii wa ni:
- Afurasí Fulani ṣekú pa ọmọ olórí ẹgbẹ́ Afẹ́nifẹ́re, Fasoranti
- Àwa ọba alayé ń wọ́nà láti ṣẹ́ eegun ẹ̀yin ọ̀daràn Fulani - Ọọ̀ni
- Ẹ yàgò fún ìwà adìẹ dàmí lóògùn nù, màá fọ lẹ́yin lásìkò ìjà - Buhari
- Ǹjẹ́ ẹ mọ ohun tí igbákejì ààrẹ Yemi Osinbajo sọ nílé bàbá Fasoranti
- Ọlọ́pàá, a fún yín ní gbèdéke ọjọ́ 21 láti mú àwọn tó pa ọmọ Fasoranti - OPC















