RUGA: Afenifere, Kunle Akinjide sọ̀rọ̀ lórí ìkéde ìjọba àpapọ̀ láti dáwọ́ dúró lórí RUGA

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Lẹyin ti aarẹ Buhari ti kede pe ijọba apapọ yoo jami lori igbesẹ ati da awọn Gaa darandaran RUGA silẹ bayii, ẹgbẹ Afẹnifẹre ti pariwo sita pe ete lasan ni ọrọ naa nitori kii ṣe pe aarẹ ni awọn wọgile e patapata.
Ẹgbẹ Afẹnifẹre ṣalaye pe niwọn igba ti ijọba apapọ ba ṣi ni i lero ati gbe igbesẹ naa dide lọjọ iwaju, awọn ko lee fi gbogbo ara dunnu si ikede naa.
Ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ lọjọbọ, agbẹnusọ fun ẹgbẹ Afẹnifẹre, Yinka Odumakin wi pe ẹtan ni ikede ijọba apapọ naa nitori kii ṣe ijọba apapọ wọgile igbesẹ naa patapata, wọn kan n jawọ lori rẹ fun igba diẹ lasan ni.
Bakan naa ni ẹgbẹ naa tun kọminu lori ẹgbẹ kan ti wọn ni o dide lapa oke Ọya to n fun ijọba apapọ ni gbedeke ọgbọn ọjọ lati bẹrẹ eto RUGA ni gbogbo ipinlẹ Naijiria bi wọn ko ba fẹ ki awọn dana wahala silẹ.
O ni ohun ti o lee dun mọ ilẹ Yoruba ninu ni ki wọn wọgile eto naa patapata.
Ninu ọrọ tirẹ, akọwe agba ẹgbẹ awọn agba ilẹ Yoruba, YCE, Dokita Kunle Ọlajide ni igbesẹ to dara ni aarẹ gbe ṣugbọn o tun ku ni ibọn n ro.
Gẹgẹ bii ifọrọwerọ Dokita Akinjide pẹlu BBC News Yoruba, o ni o yẹ ki ijọba mọ pe ọrọ orilẹede yii ti di ti 'eyi wumi ko wu ọ'
O fi kun un pe atunto orilẹede Naijiria nikan ni ọna abays fun irufẹ edeaiyede ati awuyewuye bayii.














