RUGA: Gbogbo ọmọ Nàìjíríà ló lásẹ láti gbé ìlú tó bá wù ú - Buhari

Oríṣun àwòrán, Google
Aarẹ Muhammadu Buhari ti ke si awọn Fulani darandaran ni Guusu iwọ Naijiria lati da asẹ ẹgbẹ Northern Elders Forum (NEF) nu to ni ki wọn pada wa si oke ọya ni kiakia.
Oluranlọwọ pataki fun aarẹ Muhammadu Buhari, Garba Shehu lo fi ọrọ yii lede ninu atẹjade ti aarẹ fi sita.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Ninu atẹjade naa, Aarẹ Buhari ni gbogbo ọmọ Naijiria lo ni anfaani ati eto lati rin kaakiri agbeegbe ti o ba wu wọn, tabi ki wọn gbe nibẹ.
Aarẹ Buhari ni iwe ofin orilẹede Naijiria, ijọba Naijiria ati isejọba Aarẹ Muhammadu Buhari yoo da abo bo awọn ọmọ Naijiria ni ibikibi ti wọn ba wa.
Laipẹ yii ni Ajọ Northern Elders Forum (NEF) ke si awọn darandaran Fulani kí wọ́n padà sókè ọya ní kíákíá pé ẹmi wọn ati dukia lee wa lewu ni iha Guusu ti wọn wa.









