Yellow Fever in Nigeria: Àrún ibà pónjú ti pa ènìyàn 172 ni Nàìjíríà - WHO

Oríṣun àwòrán, WHO
Ààrùn ibà pónjú tó bẹ́ sílẹ̀ lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà láìpẹ́ yìí tí mú ẹ̀mí ènìyàn méjìléláàdọ́jọ lọ báyìí.
Ààrùn yiì tún ti mú ìpèníjà míràn bá ètò ìlera orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tó sì ń tiraka láti bọ́ lọ́wọ́ ààrùn Covid-19 to ti n da gbogbo àgbáyé láàmú láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 2020.
Àjọ ìsọ̀kan àgbáyé fún ètò ìlera (WHO) sọ pé oníruurú ààrùn ló tí n yọjú láti ìbẹ̀rẹ̀ ajákàll ààrùn Covid-19 ni ìhà àríwá-ìlààoòrùn ilẹ̀ Nàìjíríà.
- Àwọn agbègbè tí àtùndi ìbò yóò kàn lọ́jọ́ Àbámẹ́ta nípìnlẹ̀ Eko rèé
- Adolf Hitler gbé àpótí ìbò, aráàlú yàn án sípò gẹ́gẹ́ bíi Káńsílọ̀
- Àwọn ohun tó bá lè fa ìwà ọ̀daràn bíi aṣọ ìwọ̀kuwọ̀ ló yẹ ká ti ọwọ́ rẹẹ̀ baṣọ - Amotekun Osun
- Díẹ̀ ló kù kí ọjọ́ ìkúnlẹ̀ di ọjọ́ ikú fún ìyá mi lọ́jọ́ tó bí mi - Seyi Makinde
Agbẹnusọ àjọ ìsọkan agbáyé fún ètò ìlera (WHO) Tarik Jasarevic sọ pé láti ọdún 2017, orílẹ̀-èdè Nàìjíríà kò tí jàjàbọ́ lọ́wọ́ ààrùn iba pójú (Yellow Fever). Èyí tó tún ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ yìí fojú hàn nínú oṣù kọkanla ọdún yìí.
Kí oṣù kọkànlá ọdún tó parí, ààrun náà ti tan ka ìpínlẹ̀ márún ni Nàìjíríà, Delta, Enugu, Benue, àti Ebonyi.
Ènìyàn ọgbọ̀n lé ẹ̀ẹ̀dẹ́gbẹ̀ta ló ti fojú hàn, tí àyẹ̀wò sì ti fìdí méjìdíláàdọ́ta múlẹ pé wọn ni ààrùn náà.
Agbẹnusọ náà sàlàyé pé, ọ̀rọ̀ Covid-19 ni ìjọba Nàìjíríà gbájú mọ́, tí wọ́n ko si ṣe àyẹwò fún àwọn ènìyàn lórí ààrùn ibàpójú.
Ó fi kún pé ní báyìí ìpińlẹ̀ mẹ́rìndílógún nínú mẹ́rìndínlógójì ló ti pari ìpolongo abẹ́rẹ́ àjẹsára ààrún ibà pọ́jú.
Àwọn ìpínlẹ̀ mẹ́fà míran yóò bẹ̀rl tiwọn ní sáà akọ́kọ́ nínú ọdún 2021.
Kó sí ìtọ́jú kan pàtó fún ààrún ibà pójú, ẹfọn sì ló máa n gbée láti ara ẹnikan si ara ẹlòmíràn.



















