Back to sender charm kills 10 in Kwara: Wọ́n ní Okosi Musa àti Worugura Julin ló fún obìnrin kan ni PENNIA Bonnie ni gàá àwọn Fulani

Oríṣun àwòrán, @Abdulrazak
Ọwọ́ sìkún ọlọ́pàá tí tẹ àwọn méjì kan lórí aburú tó wáyé ní abúlé Biogberu ni Gwanara níjọba ìbílẹ̀ Baruten ìpínlẹ̀ Kwara.
Iṣẹlẹ yii níbi tí ènìyàn mẹ́waa tí jẹ́ Ọlọ́run nípè lẹ́yìn tí wọ́n mu àgbo ìbílẹ̀.
Iṣẹ̀lẹ̀ tó wáyé ní abúlé kan lọ́jọ́ Eti tó kọjá ṣùgbọ́n ọjọ́ Isegun ni wọ́n tó mẹ́jọ́ lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́pàá.
Àwọn tọkọ taya àti àwọn ọmọ wọn tó fi mọ́ àwọn mọ̀lẹ́bí wọn ní ọ̀rọ̀ náà kàn.
- Sàárè òkú 750 dédé wú jádé níléèwè agbo-ilé kan, ìlú dàrú!
- Ẹ̀yin ọmọ Yoruba, ẹ múra láti dìbò ''referendum'' kúrò ní Naijiria, ìjọ̀ba àpapọ̀ à ń bò- Banji Akintoye
- Mo nírètí pé Baba Ijẹsha yóò gba béèlì ní iléẹjọ́ tí yóò tí farahàn lónì - Yomi Fabiyi
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo àti àwọn ẹlẹ́sìn àbáláyé bẹ̀rẹ̀ àjọṣepọ̀ láti fí opin sí ìṣoro ètò aàbò
- Wo àwọn ìlànà tí ó máa tẹ̀lé láti wo èsì ìdánwò 2021 Jamb UTME rẹ lórí ayélujára àti SMS
Ìròyìn sọ pé ara ìlú méjì kan Okosi Musa àti Worugura Julin ni wọ́n fún obìnrin kan ni PENNIA Bonnie ni gàá àwọn Fulani ni Biogberu gẹ́gẹ́ bí òògùn fún ẹsẹ̀ tó ń dùn.
Wọ́n ni wọ́n gbáà nímọ̀ran bákan náà láti fún gbogbo ẹbí rẹ ki nǹkan tó ń ṣe máa bá má tàn ká àwọn ẹbí tó kù.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
- Ẹ̀yin ọmọ Yoruba, ẹ múra láti dìbò ''referendum'' kúrò ní Naijiria, ìjọ̀ba àpapọ̀ à ń bò- Banji Akintoye
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo àti àwọn ẹlẹ́sìn àbáláyé bẹ̀rẹ̀ àjọṣepọ̀ láti fí opin sí ìṣoro ètò aàbò
- Wo àwọn ìlànà tí ó máa tẹ̀lé láti wo èsì ìdánwò 2021 Jamb UTME rẹ lórí ayélujára àti SMS
- Baba Ijesha yóò tún farahàn nílé ẹjọ́ mìí lónìí lórí ẹ̀sùn fífi ipá bá ọmọdé lòpọ̀
- Yinka Alaṣeyori fi ọ̀rọ̀ ìjínlẹ̀ púpọ̀ àti omijé ṣàlàyé Oniduro Mi
- Mo nírètí pé Baba Ijẹsha yóò gba béèlì ní iléẹjọ́ tí yóò tí farahàn lónì - Yomi Fabiyi
Ilorin: Èèyàn mẹ́wàá dèrò ọ̀run lẹ́yìn tí wọ́n mu àgbo fún ìtọ́jú egbò ẹsẹ̀ Musa n'Ilorin
'Òògùn ìtọ́jú egbò ni Musa pe àgbo tó fún mi, àmọ́ èèyàn mẹ́wàá ti kú lẹ́yìn tí wọ́n lò ó'
"Agbo ni wọn lawọn gbe wa fun iya mi ti ẹsẹ n dun, ṣugbọn eeyan mẹwaa lo kan agbako iku lẹyin ti wọn jijọ lo agbo naa".
Iroyin kayeefi ti o tun tẹ wa lọwọ ree lati ilu Biogberu ni Gwanara, ipinlẹ Kwara.
Ninu iṣẹlẹ yii la ti gbọ pe eeyan mẹwaa ninu mọlẹbi kan ti dero ọrun lẹyin ti ẹni tẹsẹ n dun kan ati awọn ẹlomiran ninu idile rẹ lo agbo.
- Ìyàwó Ooni Ogunwusi, Olori Naomi Silekunola lọ ibi ìsọmọlórúkọ Kemisola, ayé gbọ́!
- Yinka Alaṣeyori fi ọ̀rọ̀ ìjínlẹ̀ púpọ̀ àti omijé ṣàlàyé Oniduro Mi
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ń kí Kemisola kú oríire ìkómọjáde ọmọ tó bí sọ́gbà ẹ̀wọ̀n lónìí
- Èèmọ́! agbébọn jí Olóyè Tafa àti ìyàwó rẹ́ gbé nílu Ibadan
- Buhari kéde Buratai ati Olonisakin gẹ́gẹ́ bíi aṣojú Naijiria sí Republic of Benin àti Cameroun
Ninu atẹjade ti ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kwara fi fidi ọrọ yii mulẹ, wọn ni arakunrin kan Ibrahim Bonnie lo wa fi ẹjọ iṣẹlẹ naa sun lagọ ọlọpaa Biogberu.
Gẹgẹ bi alukoro ọlọpaa Kwara Okasanmi Ajayi ṣe sọ, o ni Ibrahim sọ pe Okosi Musa ati Worugura Junlin ni wọn gbe agbo naa wa ba iya oun ti o ni egbo lẹsẹ.
Ibrahim ṣalaye pe wọn ni oogun iwosan egbo ni agbo yi jẹ ati pe ki mama rii pe awọn mọlẹbi rẹ naa mu ninu agbo yii ki aisan ọhun baa ma tan d'ọdọ wọn.
- Kàyéèfì! Òkú 'jinde' ní mọ́ṣúárì!
- 'Ohun táá ṣe rèé bẹ́ẹ bá kọ̀ láti wá gbé àwọn òkú yín kúrò ní Mọ́ṣúárì wa'
- Ọlọ́jọ́ padà dé! Arákùnrin tó 'jíǹde' ní mọ́ṣúárì tí kú
- Màálù tí Ojo fẹ́ fi ṣègbeyàwó ló fẹ́ lọ rà tí wọ́n fi pà á, ti wọ́n gé ẹ̀yà ara rẹ̀ ní Kwara
- Ọlọ́pàá mẹ́rin d‘òkú lásìkò tí wọn wọ̀yá ìjà pẹ̀lú agbébọn
Ko pẹ si igba ti wọn lo agbo yii tan lawọn eeyan inu mọlẹbi yii ba bẹrẹ si ni ku lọkọọkan.
Alukoro ọlọpaa sọ pe ni meni meji, eeyan mẹwaa to fi mọ ẹni ti wọn ni ko fi agbo tọju egbo lo ti dero ọrun.
Okasanmi fi kun un pe Kọmisana ọlọpaa Kwara Mohammed Lawal Bagega ti ni ki iwadii bẹrẹ ni bonkẹlẹ.
- Òjò rọ jẹ̀jẹ̀rẹ̀ n'ílé aṣòfin Abuja, ẹ wo bí gbogbo òrùlé ṣe gbe ojò wọlé
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ń kí Kemisola kú oríire ìkómọjáde ọmọ tó bí sọ́gbà ẹ̀wọ̀n lónìí
- Èèmọ́! agbébọn jí Olóyè Tafa àti ìyàwó rẹ́ gbé nílu Ibadan
- Buhari kéde Buratai ati Olonisakin gẹ́gẹ́ bíi aṣojú Naijiria sí Republic of Benin àti Cameroun
Bẹẹ lo ni awọn ti fi awọn afurasi meji to gbe agbo naa wa si ahamọ ti wọn si ti n ran ọlọpaa lọwọ ninu iwadii wọn.
O wa rọ awọn araalu paapa ara ilu ti iṣẹlẹ naa ti waye lati tọ awọn onimọ ilera lọ nigbakigba ti wọn ba ni ailera kankan.

Oríṣun àwòrán, others
Saaju ni wọn ti ba oku ni iyara itura ni Ilorin:
Wọ́n bá òkú ọmọbìnrin nínú ilé ìtura ní Ilorin lẹ́yìn tí ọkùnrin tó gba yáàrá sálọ
Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Kwara ti kede oku obinrin kan ti wọn ri ni ile itura Premium Diamond Hotel, to wa ni adugbo Adewole nilu Ilorin.
Iroyin sọ pe ọkunrin kan to pe ara rẹ ni Adegboye James, to ni oun wa lati nọmba 12, Okelowo Street, Ede, nipinlẹ Osun, lo gba yara naa lọjọ kejidinlọgbn, oṣu Karun-un, ọdun 2021.
Amọ, o pada jade lọ, to si pada si ile itura naa pẹlu obinrin ti wọn pada ba oku rẹ ninu yara.
Ẹni to jẹ alamojuto ile itura naa, Olalekan Anafi, la gbọ pe o fi ọrọ to awọn ọlọpaa leti lẹyin ti wọn fi kọkọrọ mii ṣi ilẹkun yara naa.
Nigba ti wọn ko gburo ẹnikẹni lara awọn mejeeji ni ọjọ keji, ti wọn si ṣi ilẹkun ni wọn ba oku obinrin ọhun, ko to o di pe wọn mọ pe ọkunrin naa (Adegboye) ti kuro nile itura lai si ẹni to mọ.
- Ọkùnrin tó bẹ́ sì òdò ọ̀sà pa ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀, lòun náà fi fẹ́ kú - Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
- Ìtàn nípa orúkọ àdúgbò tó níí ṣe pẹ̀lú ìjà Oyo, Fulani àti Ilorin ní 1835
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí olóògùn owó tó fẹ́ gé ọmú obìnrin kan nílé ìtura
- Kí ló fa ikú akẹ́kọ̀ọ́ ẹni ọdún 23 yìí tí ọlópàá ba oku rẹ̀ nílé ìtura?
- Lẹ́yìn ìjà tò gbẹ̀mí èèyàn bíi mẹ́ta, Makinde sè ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ àlákòóso Amọtẹkun
- Ọ̀run àpáàdì ń dúró de gbogbo ẹ̀yin aláìní ìrònúpìwàdà- Fani Kayode sí Gumi
Agbẹnusọ ọlọpaa nipinlẹ naa, Ajayi Okasanmi to fidi iṣẹlẹ naa mulẹ fun BBC Yoruba sọ pe iwadii fihan pe ayederu ni orukọ ati adirẹsi ti Ọgbẹni Adegboye James kọ silẹ nile itura Premium Diamond.
Bakan naa lo sọ pe gbogbo nkan ti wọn fi le da obinrin naa mọ tabi ṣawari ẹbi rẹ, bi foonu, ni ọkunrin naa ko salọ.
O fikun ọrọ rẹ pe ko si àpá tabi ẹjẹ lara obinrin naa.
Agbenuso ṣalaye pe iwadii ṣi n lọ lọwọ, paapaa nipa yiyẹ ẹrọ ayaworan CCTV to wa nibẹ wo, botilẹ jẹ pe o ni ẹyin ni ọkunrin naa kọ si ẹrọ ayaworan.
Bakan naa lo tun kesi awọn araalu ti mọlẹbi wọn obinrin ba di awati lati ọjọ ti iṣẹlẹ naa waye, lati lọ si ẹka to n wadii iwa ọdaran ni olu ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kwara.
- Ṣé lóòtọ́ ni olè kan wọlè fipá bá ìyá 80 lòpọ̀ nípìnlẹ̀ Ondo?
- A ti fi páńpẹ́ ọba mú ènìyàn mẹ́ta lórí ìpànìyàn tó wáyé ní Iwo Road, Ibadan - Ọlọ́pàá
- Alága ìjọba ìbílẹ̀ Eti-Osa, Eko tí jádé láyé lẹ́yìn tó ṣe àìsàn
- Kò sí ìpínlẹ̀ tí ijọba mi kò tíì fọwọ́ bà sí rere- Ààrẹ Muhammadu Buhari
- Ẹranko àìmọ́ kan wọ Nàìjíríà, ó pa ènìyàn mẹ́rin ní Benue- ilé iṣẹ́ ọmọogun ni ìròyìn òfegè ni
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ń kí Kemisola kú oríire ìkómọjáde ọmọ tó bí sọ́gbà ẹ̀wọ̀n lónìí

















