Fact Check: Ẹranko àìmọ́ kan wọ Nàìjíríà, ó pa ènìyàn mẹ́rin ni Benue- ilé iṣẹ́ ọmọogun ni ìròyìn òfegè ni

Oríṣun àwòrán, others
Ilé iṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà tí sọ fún àwọn ènìyàn láti keti ìkún sì fọnran kan tó safihan ẹranko àìmọ tó ń jà rainrain lórí ayélujára.
Lójú òpó ìkànsíraẹni Facebook wọn ní wọ́n tí sàfihan rẹ bí ìròyìn òfégè ni, àtẹ̀jáde náà sọ pé àwọn ọmọogun pá ẹranko àìmọ kan ni ìpínlẹ̀ Benue.
- Kò sí ìpínlẹ̀ tí ijọba mi kò tíì fọwọ́ bà sí rere- Ààrẹ Muhammadu Buhari
- Alága ìjọba ìbílẹ̀ Eti-Osa, Eko tí jádé láyé lẹ́yìn tó ṣe àìsàn
- A ti fi páńpẹ́ ọba mú ènìyàn mẹ́ta lórí ìpànìyàn tó wáyé ní Iwo Road, Ibadan - Ọlọ́pàá
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ ẹni ọdún 40 tó fipá bá ìyá ọdún 60 lòpọ̀ ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Ajínigbe sún gbàgbé láwọn 15 nínú àwọn 156 tí wọ́n jí gbé ní Tegina bá sálọ
- Wo ìdí tí EFCC fi fẹ́ wádìí ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Ogun láti ọdun 2015 dí àsìkò yìí
- Father's Day fa gbas-gbos láàrin Mercy Aigbe àti ọkọ rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Gentry, ọkọ́ ní òun le tú àwọn àṣírí ìwà nọ̀bì rẹ̀ síta
Ìròyìn náà ni pé fọ́nrán kan ń jà rainrain lópin ọ̀sẹ̀ tó kọjá èyí tí ọ̀pọ̀ sì gbàgbọ́ pé ajá igbó ni lóòótọ́.
"Nǹkan tó jọ ajá igbó sì sùn silẹ tó nínú fọ́nrán náà tí ọkùnrin kan sì ń sọ èdè Pidgin pé tí wọn ba ni kí ẹ dúró sílè yín ẹ ó ní gbọ́

Oríṣun àwòrán, @DHQ
Fọ́nrán náà kan gbogbo àwọn ènìyàn nítorí pé wọ́n ń ìgbàgbọ́ pé ìkòkò tí wọ orileede yii.
Ṣùgbọ́n ilé iṣẹ́ ọmọogun sọ pé ìròyìn òfégè ni.
"Àtẹ̀jáde àti fọ́ran to lọ ká lórí ayélujára nípa ẹranko abàmì kan tó ní ara ènìyàn tí ọkàn nínú àwọn ọmọogun ikọ operation whirl stroke kíi ṣe ootọ́.
Wọn ni ojúlówó fọ́nrán náà jẹ ti eré sinima "Lobisomem Morto a Tiros".
Nínú àtẹ̀jáde ayédèrú náà ni wọ́n ti sọ pé ìlú Tempele lọ tí ṣẹlẹ̀ nípìnlẹ̀ Benue pé àwọn kan ló tá ikọ ọmọogun náà lolobo ri wọn sì pá ẹranko ọ̀hún.
Ile isẹ ọmọogun Naijiria ni, ẹni tó gbé ìròyìn ayédèrú náà síta ni Nàìjíríà gbé ohùn rẹ lè ojúlówó ohun tó wà nínú fọnran tí Cloud Wold ṣe.
- Wo ìdí tí EFCC fi fẹ́ wádìí ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Ogun láti ọdun 2015 dí àsìkò yìí
- 'Kò sí ẹni tó lè ní kí a má wá sí Èkó, iwọ́de òní pẹ̀lẹ́ kùtù la fẹ́ ṣe'
- Kò sí ìpínlẹ̀ tí ijọba mi kò tíì fọwọ́ bà sí rere- Ààrẹ Muhammadu Buhari
- Àlàyé rè é lórí bí o ṣe lè gbá owó ìrànwọ́ N50bn COVID-19 tí CBN gbé jáde
- Lẹ́yìn ìjà tò gbẹ̀mí èèyàn bíi mẹ́ta, Makinde sè ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ àlákòóso Amọtẹkun














